< Psalms 21 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ, àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
Przedniejszemu śpiewakowi pieśń Dawidowa. Panie! w mocy twojej raduje się król, a w zbawieniu twojem wielce się weseli.
2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. (Sela)
Dałeś mu żądość serca jego, a prośby ust jego nie odmówiłeś mu. (Sela)
3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
Albowiemeś go uprzedził błogosławieństwy hojnemi; włożyłeś na głowę jego koronę ze złota szczerego.
4 Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un, àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
Prosił cię o żywot, a dałeś mu przedłużenie dni na wieki wieków.
5 Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un; ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
Wielka jest chwała jego w zbawieniu twojem; chwałą i zacnością przyodziałeś go;
6 Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un: ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
Boś go wystawił na rozmaite błogosławieństwo aż na wieki; rozweseliłeś go weselem oblicza twego.
7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa; nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà kì yóò sípò padà.
Gdyż król nadzieję ma w Panu, a z miłosierdzia Najwyższego nie będzie poruszony.
8 Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
Znajdzie ręka twoja wszystkich nieprzyjaciół twoich, prawica twoja dosięże wszystkich, co cię w nienawiści mają.
9 Nígbà tí ìwọ bá yọ ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru. Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀, àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
Uczynisz ich jako piec ognisty czasu gniewu twego; Pan w popędliwości swojej wytraci ich, a ogień ich pożre.
10 Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀, àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
Plemię ich z ziemi wygubisz, a nasienie ich z synów ludzkich.
11 Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
Albowiem czyhali na twoje złe; zmyślali radę, której dowieść nie mogli.
12 Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
Przetoż wystawisz ich za cel; cięciwę twą wyciągniesz przeciwko twarzy ich.
13 Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ; a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.
Podnieśże się, Panie! w mocy twojej, tedy będziemy śpiewać i wysławiać możność twoję.

< Psalms 21 >