< Psalms 21 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ, àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
Au maître-chantre. — Psaume de David. O Éternel, le roi se réjouit de ta force. Quelle allégresse lui donne ta délivrance!
2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. (Sela)
Tu as répondu au désir de son coeur, Et tu ne lui as pas refusé ce que ses lèvres avaient demandé. (Pause)
3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
Car tu l'as prévenu par des bienfaits excellents; Tu as mis sur sa tête une couronne d'or fin.
4 Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un, àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
Il te demandait la vie: tu la lui as accordée, Une vie dont les jours dureront à perpétuité, à jamais.
5 Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un; ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
Sa gloire est grande, grâce à ton secours victorieux; Tu le revêts de splendeur et de majesté.
6 Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un: ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
Tu fais de lui l'objet de tes bénédictions pour toujours; Tu le combles de joie devant ta face.
7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa; nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà kì yóò sípò padà.
Car le roi met sa confiance en l'Éternel, Et, par la bonté du Très-Haut, il ne chancellera point.
8 Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
Ta main atteindra tous tes ennemis; Ta main droite atteindra ceux qui te haïssent.
9 Nígbà tí ìwọ bá yọ ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru. Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀, àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
Tu les consumeras comme dans une fournaise ardente, Aussitôt que tu te montreras. L'Éternel les engloutira dans sa colère, Et le feu les dévorera.
10 Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀, àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
Tu feras disparaître de la terre leur postérité, Et leur race du milieu des fils des hommes.
11 Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
Ils ont projeté du mal contre toi; Ils ont formé de méchants desseins: ils ne pourront les exécuter;
12 Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
Car tu les mettras en fuite. Tu dirigeras ton arc contre eux.
13 Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ; a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.
Lève-toi, ô Éternel, dans ta force! Nous chanterons et nous célébrerons tes exploits.

< Psalms 21 >