< Psalms 21 >
1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ, àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
Au maître chantre. Cantique de David. Éternel, ta puissance donne au Roi de la joie, et comme ton secours le transporte!
2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. (Sela)
Tu as satisfait au désir de son cœur, et tu n'as point rebuté la prière de ses lèvres. (Pause)
3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
Tu lui as présenté des biens excellents, et tu as mis sur sa tête un diadème d'or.
4 Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un, àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
Il te demandait la vie; tu la lui as donnée, une vie longue, permanente, éternelle.
5 Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un; ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
Sa gloire est grande, grâce à ton secours, et tu lui accordes splendeur et majesté;
6 Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un: ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
car tu le rends béni éternellement, tu le réjouis du bonheur de ta présence.
7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa; nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà kì yóò sípò padà.
Car le Roi se confie en l'Éternel, et, par la faveur du Très-haut, il n'est point ébranlé.
8 Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
Ta main saura trouver tous tes ennemis, et ta droite trouvera ceux qui te sont hostiles.
9 Nígbà tí ìwọ bá yọ ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru. Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀, àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
Tu les rendras pareils à une fournaise ardente, dès que tu te montreras; l'Éternel dans son courroux les détruira, et ils seront consumés par le feu;
10 Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀, àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
de la terre tu extermineras leur fruit, et leur race, d'entre les fils des hommes;
11 Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
parce qu'ils ourdirent contre toi les trames de la malice, et formèrent des complots: ils seront impuissants;
12 Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
car tu leur feras prendre la fuite, et tu dirigeras ton arc contre leurs faces.
13 Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ; a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.
Lève-toi, Éternel, avec ta puissance! Nous voulons chanter et célébrer tes hauts faits.