< Psalms 21 >
1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ, àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
Jusqu'à la Fin, psaume de David. Seigneur, le roi se réjouira de ta puissance; il sera, dans l'excès de sa joie, sauvé par toi.
2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. (Sela)
Tu l'as gratifié selon les désirs de son âme; tu ne l'as point sevré de ce que demandaient ses lèvres.
3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
Tu l'as prévenu des bénédictions de ta douceur; tu as posé sur sa tête une couronne de pierres précieuses.
4 Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un, àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
Il t'a demandé la vie, et tu lui as donné de longs jours qui s'étendront dans tous les siècles, des siècles.
5 Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un; ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
Sa gloire est grande d'avoir été sauvé par toi; tu as mis sur lui la gloire et la magnificence.
6 Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un: ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
Car tu le béniras dans tous les siècles des siècles; tu le combleras de joie en lui montrant ta face.
7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa; nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà kì yóò sípò padà.
Aussi le roi espère dans le Seigneur; grâce à la miséricorde du Très- Haut, il ne sera jamais ébranlé.
8 Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
Que tous tes ennemis trouvent ta main; que ta droite trouve tous ceux qui te haïssent.
9 Nígbà tí ìwọ bá yọ ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru. Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀, àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
Au temps où ta face se tournera contre eux, tu les brûleras comme dans une fournaise embrasée; le Seigneur les troublera de sa colère, et le feu les dévorera.
10 Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀, àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
Tu détruiras leurs fruits sur la terre, et leurs fils d'entre les fils des hommes,
11 Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
Parce qu'ils ont voulu déverser sur toi le mal; ils ont conçu des desseins dont ils ne pourront venir à bout.
12 Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
Aussi tu leur feras tourner le dos; et pour recevoir tes derniers coups, tu retourneras leur visage.
13 Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ; a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.
Lève-toi, Seigneur, en ta force; nous célébrerons et nous chanterons tes grandeurs.