< Psalms 21 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Háà! Olúwa, ọba yóò yọ̀ nínú agbára rẹ, àti ní ìgbàlà rẹ, yóò ti yọ̀ pẹ́ tó!
To him that excelleth. A Psalme of Dauid. The King shall reioyce in thy strength, O Lord: yea how greatly shall he reioyce in thy saluation!
2 Nítorí pé ìwọ ti fi ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ fún un, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì dùn ún ní ìbéèrè ẹnu rẹ̀. (Sela)
Thou hast giuen him his hearts desire, and hast not denyed him the request of his lips. (Selah)
3 Ìwọ ti fi àwọn ìbùkún oore kò ó ni ọ̀nà ìwọ fi adé wúrà dé e ní orí.
For thou diddest preuent him with liberall blessings, and didest set a crowne of pure gold vpon his head.
4 Ó béèrè fún ìyè, ìwọ sì fi fún un, àní ọjọ́ gígùn títí ayérayé.
He asked life of thee, and thou gauest him a long life for euer and euer.
5 Ògo rẹ̀ pọ̀ nípasẹ̀ ìṣẹ́gun tí o fi fún un; ìwọ sì jẹ́ kí iyì ọláńlá rẹ̀ wà lára rẹ.
His glory is great in thy saluation: dignitie and honour hast thou laid vpon him.
6 Dájúdájú, ìwọ ti fi ìbùkún ayérayé fún un: ìwọ sì mú inú rẹ̀ dùn pẹ̀lú ayọ̀ ojú u rẹ̀.
For thou hast set him as blessings for euer: thou hast made him glad with the ioy of thy countenance.
7 Ọba ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa; nípasẹ̀ ìfẹ́ Ọ̀gá-ògo tí kì í kùnà kì yóò sípò padà.
Because the King trusteth in the Lord, and in the mercie of the most High, he shall not slide.
8 Ọwọ́ rẹ yóò wá gbogbo àwọn ọ̀tá a rẹ rí; ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò wá àwọn tí o kórìíra rẹ rí.
Thine hand shall finde out all thine enemies, and thy right hand shall finde out them that hate thee.
9 Nígbà tí ìwọ bá yọ ìwọ yóò mú wọn dàbí iná ìléru. Olúwa yóò gbé wọn mì nínú ìbínú rẹ̀, àti pé iná rẹ̀ yóò jó wọn run.
Thou shalt make them like a fierie ouen in time of thine anger: the Lord shall destroy them in his wrath, and the fire shall deuoure them.
10 Ìwọ yóò pa ìrandíran wọn run kúrò lórí ilẹ̀, àti irú-ọmọ wọn kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
Their fruite shalt thou destroy from the earth, and their seede from the children of men.
11 Bí o tilẹ̀ jẹ́ wí pé wọ́n ro èrò ibi sí ọ wọ́n sì ń pète ìwà ìkà, wọn kì yóò ṣe àṣeyọrí.
For they intended euill against thee, and imagined mischiefe, but they shall not preuaile.
12 Nítorí pé ìwọ yóò mú wọn yí ẹ̀yìn wọn padà nígbà tí o bá pinnu láti ta wọ́n ní ọfà.
Therefore shalt thou put them aparte, and the strings of thy bowe shalt thou make readie against their faces.
13 Gbígbéga ni ọ́ Olúwa, nínú agbára rẹ; a ó kọrin, a ó yín agbára a rẹ̀.
Be thou exalted, O Lord, in thy strength: so will we sing and prayse thy power.

< Psalms 21 >