< Psalms 20 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Kí Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú; kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
Přednímu zpěváku, žalm Davidův. Vyslyšiž tě Hospodin v den ssoužení, k zvýšení tě přiveď jméno Boha Jákobova.
2 Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́ kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
Sešliž tobě pomoc z svatyně, a z Siona utvrzuj tě.
3 Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. (Sela)
Rozpomeniž se na všecky oběti tvé, a zápaly tvé v popel obrať. (Sélah)
4 Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
Dejž tobě vše podlé srdce tvého, a všelikou radu tvou vyplň.
5 Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa. Kí Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
I budeme prozpěvovati o spasení tvém, a ve jménu Boha našeho korouhve vyzdvihneme; naplniž Hospodin všecky prosby tvé.
6 Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé, Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́. Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Nyníť jsme poznali, že Hospodin zachoval svého pomazaného, a že jej vyslyšel s nebe svatého svého; nebo v jeho přesilné pravici jest spasení.
7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin, ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
Tito v vozích, jiní v koních doufají, ale my jméno Hospodina Boha našeho sobě připomínáme.
8 Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú, ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
A protož oni sehnuti jsou, a padli, ale my povstali jsme, a zmužile stojíme.
9 Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba! Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!
Hospodine, zachovávejž nás, i král ať slyší nás, když k němu volati budeme.

< Psalms 20 >