< Psalms 20 >
1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Kí Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú; kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
Kathutkung: Devit Runae hnin dawk BAWIPA ni na pato naseh. Jakop Cathut min lahoi na roum sak naseh.
2 Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́ kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
Hmuen kathoung koehoi kabawpnae teh tâcawt sak naseh. Zion hoi tha awm sak naseh.
3 Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. (Sela)
Na thuengnae pueng na thai pouh naseh. Hmaisawi thuengnae hai dâw naseh.
4 Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
Na ngainae patetlah na poe naseh, na pouknae patetlah kuep sak naseh.
5 Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa. Kí Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
Na rungngangnae dawk ka konawm awh vaiteh, Cathut min lahoi lukkarei a yap awh han. BAWIPA ni na hei e pueng kuep sak lawiseh.
6 Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé, Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́. Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
BAWIPA ni satui awi e a rungngang tie atuvah panue awh toe. Kathounge kalvan hoi a rungngangnae aranglae kut, athakaawme hoi na pato han.
7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin, ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
Atangawn ni leng a kâuep awh teh, atangawn ni marang a kâuep awh. Hatei, kaimouh teh, BAWIPA Cathut min hah pou ka kâuep awh han.
8 Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú, ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
Ahnimouh teh tabut hoi a rawp awh. Hatei, kaimouh teh ka thaw awh teh, kalancalah ka kangdue awh.
9 Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba! Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!
BAWIPA rungngang haw. Ka kaw toteh siangpahrang ni na pato naseh.