< Psalms 20 >
1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Kí Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú; kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.
Si Jehova motubag kanimo sa adlaw sa kasamok; Ang ngalan sa Dios ni Jacob magatuboy kanimo sa itaas;
2 Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́ kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.
Magapadala kanimo ug tabang gikan sa balaang puloy-anan, Ug gikan sa Sion pagalig-onon ikaw;
3 Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. (Sela)
Hinumduman mo ang tanan mong mga halad, Ug dawaton ang imong halad-nga-sinunog; (Selah)
4 Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.
Hatagan ikaw ingon sa tinguha sa imong kasingkasing, Ug tumanon ang bug-os mong tambag.
5 Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa. Kí Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.
Kami makadaug diha sa imong kaluwasan, Ug sa ngalan sa among Dios, magapakayab kami sa among mga bandila: Si Jehova magatuman sa tanan mong mga pangayo.
6 Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé, Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́. Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Karon nahibalo ako nga si Jehova nagaluwas sa iyang dinihog; Siya magatubag kaniya gikan sa iyang langit nga balaan Uban sa kusog sa kaluwasan sa iyang toong kamot.
7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin, ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.
Ang uban nagasalig sa mga carro, ug ang uban sa mga kabayo; Apan kami magahisgut sa ngalan ni Jehova nga among Dios.
8 Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú, ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.
Ginapaluhod (sila) ug nangapukan; Apan kami nagatindog, ug nagabarug nga matul-id.
9 Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba! Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!
Luwasa, Oh Jehova: Patubaga ang Hari, sa diha nga magatawag kami kaniya.