< Psalms 2 >

1 Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀, àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?
Pentru ce se înfurie păgânii și își închipuie popoarele deșertăciune?
2 Àwọn ọba ayé péjọpọ̀ àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀ sí Olúwa àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.
Împărații pământului se ridică și conducătorii țin sfat împreună împotriva DOMNULUI și împotriva unsului său, spunând:
3 Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já, kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
Să le rupem în bucăți legăturile și să le aruncăm funiile de la noi.
4 Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
Cel ce șade în ceruri va râde; Domnul îi va lua în derâdere.
5 Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀ yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,
Apoi le va vorbi în furia lui și îi va chinui în aprinderea sa.
6 “Èmi ti fi ọba mi sí ipò lórí Sioni, òkè mímọ́ mi.”
Totuși, eu mi-am înălțat pe împăratul peste muntele meu sfânt al Sionului.
7 Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa: Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí, èmi ti di baba rẹ.
Voi vesti hotărârea, DOMNUL mi-a spus: Tu ești Fiul meu; astăzi te-am născut.
8 Béèrè lọ́wọ́ mi, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ, òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.
Cere-mi și îți voi da păgânii drept moștenire și cele mai îndepărtate margini ale pământului drept stăpânire.
9 Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀.”
Tu îi vei zdrobi cu un toiag de fier și îi vei sparge în bucăți ca pe vasul unui olar.
10 Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n; ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
De aceea fiți înțelepți împăraților; instruiți-vă voi judecători ai pământului.
11 Ẹ sin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rù ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.
Serviți DOMNULUI cu teamă și bucurați-vă tremurând.
12 Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú, kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín, nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.
Sărutați pe Fiul ca să nu se mânie și să pieriți pe cale, când furia lui abia s-a aprins. Binecuvântați sunt toți cei ce își pun încrederea în el.

< Psalms 2 >