< Psalms 2 >

1 Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀, àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?
Miért csődültek a népek, és gondolnak hiábavalót a nemzetek,
2 Àwọn ọba ayé péjọpọ̀ àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀ sí Olúwa àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.
összeállanak a föld királyai, és együtt tanakodnak a fejedelmek az Örökkévaló és az ő fölkentje ellen?
3 Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já, kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
Szakítsuk szét kötelékeiket, s vessük le magunkról bilincseiket!
4 Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
Az égben trónoló nevet, az Úr gúnyolódik rajtuk,
5 Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀ yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,
akkor beszél hozzájuk haragjában és hevében megrettenti őket:
6 “Èmi ti fi ọba mi sí ipò lórí Sioni, òkè mímọ́ mi.”
Hisz én iktattam be királyomat Cziónon, az én szent hegyemen. –
7 Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa: Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí, èmi ti di baba rẹ.
Hadd adok hírt törvényről! Az Örökkévaló szólt hozzám: fiam vagy, én ma szülőd lettem.
8 Béèrè lọ́wọ́ mi, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ, òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.
Kérj tőlem, s majd adok nemzeteket birtokodul s tulajdonodul a földnek végeit;
9 Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀.”
majd megtöröd őket vaspálczával, mint a fazekasedényt szétzúzod őket!
10 Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n; ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
Most tehát királyok, térjetek észre, okuljatok, földnek birái;
11 Ẹ sin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rù ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.
szolgáljátok az Örökkévalót félelemben és ujjongjatok remegés közt.
12 Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú, kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín, nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.
Hódoljatok a fiúnak, nehogy haragudjék s elvesznétek az úton; mert kevés híján felgyúl a haragja. Boldogok mind, kik benne keresnek menedéket!

< Psalms 2 >