< Psalms 2 >

1 Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀, àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?
Защо се разоряват народите, И племената намислюват суета?
2 Àwọn ọba ayé péjọpọ̀ àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀ sí Olúwa àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.
Опълчват се земните царе, И управниците се наговарят заедно, Против Господа и против Неговия помазаник, като казват:
3 Wọ́n sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já, kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù.”
Нека разкъсаме връзките им, И нека отхвърлим от себе си въжетата им.
4 Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín; Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.
Тоя, Който седи на небесата, ще се смее; Господ ще им се поругае.
5 Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀ yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,
Това ще им продума в гнева Си, И в тежкото Си негодувание ще ги смути, казвайки:
6 “Èmi ti fi ọba mi sí ipò lórí Sioni, òkè mímọ́ mi.”
Но Аз поставих Царя Си На Сион, светия Мой хълм.
7 Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa: Ó sọ fún mi pé, “Ìwọ ni ọmọ mi; lónìí, èmi ti di baba rẹ.
Аз ще изявя постановлението; Господ ми каза: Ти си Мой Син; Аз днес те родих.
8 Béèrè lọ́wọ́ mi, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ, òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.
Поискай от Мене и Аз ще ти дам народите за твое наследство, И земните краища за твое притежание.
9 Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀.”
Ще ги съкрушиш с желязна тояга, Ще ги строшиш като грънчарски съд.
10 Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n; ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.
Сега, прочее, вразумете се, о царе; Научете се земни съдии.
11 Ẹ sin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rù ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.
Слугувайте на Господа със страх, И радвайте се с трепет.
12 Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú, kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín, nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.
Целувайте Избраника, за да се не разгневи, Та погинете в пътя; Защото скоро ще пламне Неговият гняв. Блажени са всички, които се надяват на Него.

< Psalms 2 >