< Psalms 19 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Àwọn ọ̀run ń sọ nípa ti ògo Ọlọ́run; àwọsánmọ̀ ń sọ nípa ti iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
Przewodnikowi chóru. Psalm Dawida. Niebiosa głoszą chwałę Boga, a firmament obwieszcza dzieło jego rąk.
2 Wọ́n ń fọhùn ní ọjọ́ dé ọjọ́; wọ́n ń fi ìmọ̀ hàn ní alẹ́ dé alẹ́.
Dzień dniowi opowiada słowo, a noc nocy oznajmia wiedzę.
3 Kò sí ohùn tàbí èdè níbi tí a kò gbé gbọ́ ìró wọn.
Nie ma języka ani mowy, w których nie słychać ich głosu.
4 Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo orílẹ̀ ayé, ọ̀rọ̀ wọn títí dé òpin ilẹ̀ ayé. Ó ti kọ́ àgọ́ fún oòrùn nínú àwọn ọ̀run.
Ich zasięg rozchodzi się po całej ziemi i na krańce świata ich słowa. Na nich wystawił namiot słońcu.
5 Tí ó dàbí ọkọ ìyàwó tí ó ń jáde ti yàrá rẹ̀ wá, òun yọ bí alágbára ọkùnrin tí ó ń sáré ìje.
A ono wychodzi jak oblubieniec ze swojej komnaty, cieszy się jak mocarz, który rozpoczyna bieg.
6 Ìjáde lọ rẹ̀ ni láti òpin ọ̀run wá àti àyíká rẹ̀ sì dé ìpínlẹ̀ rẹ̀; kò sì sí ohun tí ó pamọ́ kúrò nínú oore rẹ̀.
Wyrusza z jednego krańca nieba i obchodzi je aż na drugi kraniec, a nic nie ukryje się przed jego żarem.
7 Pípé ni òfin Olúwa, ó ń yí ọkàn padà. Ẹ̀rí Olúwa dánilójú, ó sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.
Prawo PANA jest doskonałe, nawracające duszę; świadectwo PANA pewne, dające mądrość prostemu.
8 Ìlànà Olúwa tọ̀nà, ó ń fi ayọ̀ fún ọkàn. Àṣẹ Olúwa ni mímọ́, ó ń fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú.
Nakazy PANA [są] prawe, radujące serce; przykazanie PANA czyste, oświecające oczy.
9 Ìbẹ̀rù Olúwa mọ́, ó ń faradà títí láéláé. Ìdájọ́ Olúwa dájú òdodo ni gbogbo wọn.
Bojaźń PANA jest czysta, trwająca na wieki; sądy PANA prawdziwe, wszystkie są słuszne.
10 Wọn ṣọ̀wọ́n ju wúrà lọ, ju wúrà tí o dára jùlọ, wọ́n dùn ju oyin lọ, àti ju afárá oyin lọ.
Bardziej pożądane niż złoto, niż mnóstwo szczerego złota, i słodsze niż miód, nawet niż plaster miodu.
11 Nípa wọn ni a ti ṣí ìránṣẹ́ rẹ̀ létí; nípa pípa wọ́n mọ́, èrè púpọ̀ ń bẹ.
Także twój sługa jest przez nie pouczony, a kto ich przestrzega, otrzymuje wielką nagrodę.
12 Ta ni ó lè mọ àṣìṣe rẹ̀? Dáríjì mí nínú àṣìṣe mi tí ó pamọ́.
Lecz kto dostrzeże [własne] błędy? Oczyść mnie z [tych, które są] ukryte przede mną.
13 Wẹ ìránṣẹ́ rẹ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀ọ́n-mọ̀-dá; má ṣe jẹ kí wọn kí ó jẹ ọba lórí mi. Nígbà náà ní èmi yóò dúró ṣinṣin, èmi yóò sì ṣe aláìlẹ́bi kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
Chroń też swego sługę od zuchwałych [grzechów], aby nie panowały nade mną. Wtedy będę nienaganny i wolny od wielkiego przestępstwa.
14 Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mi kí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ, Ìwọ Olúwa àpáta mi, àti Olùdáǹdè mi.
Niech będą ci miłe słowa moich ust i rozmyślanie mego serca, PANIE, moja Skało i mój Odkupicielu!

< Psalms 19 >