< Psalms 19 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Àwọn ọ̀run ń sọ nípa ti ògo Ọlọ́run; àwọsánmọ̀ ń sọ nípa ti iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.
Přednímu z kantorů, žalm Davidův. Nebesa vypravují slávu Boha silného, a dílo rukou jeho obloha zvěstuje.
2 Wọ́n ń fọhùn ní ọjọ́ dé ọjọ́; wọ́n ń fi ìmọ̀ hàn ní alẹ́ dé alẹ́.
Den po dni vynáší řeč, a noc po noci ukazuje umění.
3 Kò sí ohùn tàbí èdè níbi tí a kò gbé gbọ́ ìró wọn.
Neníť řeči ani slov, kdež by nemohl slyšán býti hlas jejich.
4 Ohùn wọn jáde lọ sí gbogbo orílẹ̀ ayé, ọ̀rọ̀ wọn títí dé òpin ilẹ̀ ayé. Ó ti kọ́ àgọ́ fún oòrùn nínú àwọn ọ̀run.
Po vší zemi rozchází se zpráva jejich, a až do končin okršlku slova jich, slunci pak rozbil stánek na nich.
5 Tí ó dàbí ọkọ ìyàwó tí ó ń jáde ti yàrá rẹ̀ wá, òun yọ bí alágbára ọkùnrin tí ó ń sáré ìje.
Kteréž jako ženich vychází z pokoje svého, veselí se jako udatný rek, cestou běžeti maje.
6 Ìjáde lọ rẹ̀ ni láti òpin ọ̀run wá àti àyíká rẹ̀ sì dé ìpínlẹ̀ rẹ̀; kò sì sí ohun tí ó pamọ́ kúrò nínú oore rẹ̀.
Od končin nebes východ jeho, a obcházení jeho až zase do končin jejich, a ničeho není, což by se ukryti mohlo před horkostí jeho.
7 Pípé ni òfin Olúwa, ó ń yí ọkàn padà. Ẹ̀rí Olúwa dánilójú, ó sọ òpè di ọlọ́gbọ́n.
Zákon Hospodinův jest dokonalý, očerstvující duši, Hospodinovo svědectví pravé, moudrost dávající neumělým.
8 Ìlànà Olúwa tọ̀nà, ó ń fi ayọ̀ fún ọkàn. Àṣẹ Olúwa ni mímọ́, ó ń fi ìmọ́lẹ̀ fún ojú.
Rozkazové Hospodinovi přímí, obveselující srdce, přikázaní Hospodinovo čisté, osvěcující oči.
9 Ìbẹ̀rù Olúwa mọ́, ó ń faradà títí láéláé. Ìdájọ́ Olúwa dájú òdodo ni gbogbo wọn.
Bázeň Hospodinova čistá, zůstávající na věky, soudové Hospodinovi praví, a k tomu i spravedliví.
10 Wọn ṣọ̀wọ́n ju wúrà lọ, ju wúrà tí o dára jùlọ, wọ́n dùn ju oyin lọ, àti ju afárá oyin lọ.
Mnohem žádostivější jsou než zlato, a než mnoho ryzího zlata, sladší než med a stred z plástů.
11 Nípa wọn ni a ti ṣí ìránṣẹ́ rẹ̀ létí; nípa pípa wọ́n mọ́, èrè púpọ̀ ń bẹ.
Služebník tvůj zajisté jimi osvěcován bývá, a kdož jich ostříhá, užitek hojný má.
12 Ta ni ó lè mọ àṣìṣe rẹ̀? Dáríjì mí nínú àṣìṣe mi tí ó pamọ́.
Ale poblouzením kdo vyrozumí? Protož i od tajných očisť mne.
13 Wẹ ìránṣẹ́ rẹ mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àmọ̀ọ́n-mọ̀-dá; má ṣe jẹ kí wọn kí ó jẹ ọba lórí mi. Nígbà náà ní èmi yóò dúró ṣinṣin, èmi yóò sì ṣe aláìlẹ́bi kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ńlá.
I od zúmyslných zdržuj služebníka svého, aby nade mnou nepanovali, a tehdyť dokonalý budu, a očištěný od přestoupení velikého.
14 Jẹ́ kí ọ̀rọ̀ ẹnu mi àti àṣàrò ọkàn mi kí ó jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà ní ojú rẹ, Ìwọ Olúwa àpáta mi, àti Olùdáǹdè mi.
Ó ať jsou slova úst mých tobě příjemná, i přemyšlování srdce mého před tebou, Hospodine skálo má, a vykupiteli můj.

< Psalms 19 >