< Psalms 17 >

1 Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, ẹ̀bẹ̀ òtítọ́ mi; fi etí sí igbe mi. Tẹ́tí sí àdúrà mi tí kò ti ètè ẹ̀tàn jáde.
Modlitba Davidova. Vyslyš, Hospodine, spravedlnost, a pozoruj volání mého; nakloň uší k modlitbě mé, kteráž jest beze vší rtů ošemetnosti.
2 Kí ìdáláre mi wá láti ọ̀dọ̀ rẹ; kí ojú rẹ kí ó rí ohun tí ó tọ́.
Od tváři tvé vyjdiž soud můj, oči tvé nechať patří na upřímnost.
3 Ìwọ ti dán àyà mi wò, ìwọ sì bẹ̀ mí wò ní òru, o sì ti wádìí mi, ìwọ kì yóò rí ohunkóhun èmi ti pinnu pé, ẹnu mi kì yóò ṣẹ̀.
Zkusils srdce mého, navštívils je v noci; ohněm jsi mne zpruboval, aniž jsi co shledal; to, což myslím, nepředstihá úst mých.
4 Bí ó ṣe ti iṣẹ́ ènìyàn nípa ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ, èmi ti pa ara mi mọ́ kúrò ní ọ̀nà àwọn ìkà.
Z strany pak skutků lidských, já podlé slova rtů tvých vystříhal jsem se stezky zhoubce.
5 Ìrìn mí ti jẹ mọ́ ọ̀nà rẹ; ẹsẹ̀ mi kì yóò yọ̀.
Zdržuj kroky mé na cestách svých, aby se neuchylovaly nohy mé.
6 Èmi ké pè ọ́, Ọlọ́run, nítorí tí ìwọ yóò dá mi lóhùn dẹ etí rẹ sí mi kí o sì gbọ́ àdúrà mi.
Já volám k tobě, nebo vyslýcháš mne, ó Bože silný; nakloň ke mně ucha svého, a slyš řeč mou.
7 Fi ìṣeun ìyanu ìfẹ́ ńlá rẹ hàn ìwọ tí ó fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ gba àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
Prokaž milosrdenství svá, naději majících ochránce před těmi, kteříž povstávají proti pravici tvé.
8 Pa mí mọ́ bí ẹyin ojú rẹ; fi mí pamọ́ sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ apá rẹ,
Ostříhej mne jako zřítelnice oka, v stínu křídel svých skrej mne,
9 lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú tí ń fóròó mi, kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá apani tí ó yí mi ká.
Od tváři bezbožných těch, kteříž mne hubí, od nepřátel mých úhlavních obkličujících mne,
10 Wọ́n pa ọkàn aláìláàánú wọn mọ́, wọ́n sì fi ẹnu wọn sọ̀rọ̀ ìgbéraga.
Kteříž tukem svým zarostli, mluví pyšně ústy svými.
11 Wọ́n sì mú mi mọ́lẹ̀, wọ́n sì yí mi ká, pẹ̀lú ojú ìṣọ́ra láti ṣọ́ mi sílẹ̀.
Jižť i kroky naše předstihají, oči své obrácené mají, aby nás porazili na zem.
12 Wọn dàbí i kìnnìún tí ebi ń pa fún ìjẹ, àní bí kìnnìún ńlá tí ó ń ba níbi ìkọ̀kọ̀.
Každý z nich podoben jest lvu žádostivému loupeže, a lvíčeti sedícímu v skrýši.
13 Dìde, Olúwa, dojúkọ wọ́n, rẹ̀ wọ́n sílẹ̀; gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ẹni búburú nípa idà rẹ.
Povstaniž, Hospodine, předejdi tváři jeho, sehni jej, a vytrhni duši mou od bezbožníka mečem svým,
14 Olúwa, nípa ọwọ́ rẹ, gbà mí kúrò lọ́wọ́ irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀, kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn ayé yìí, tí èrè wọn wà nínú ayé yìí. Ìwọ ń pa ebi àwọn tí ìwọ fẹ́ràn lẹ́nu mọ́; àwọn ọmọ wọn sì ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, wọ́n sì kó ọrọ̀ jọ fún àwọn ọmọ wọn.
Rukou svou od lidí, ó Hospodine, od lidí světských, jichžto oddíl jest v tomto životě, a jejichž břicho ty z špižírny své naplňuješ. Èímž i synové jejich nasyceni bývají, a ostatků zanechávají maličkým svým.
15 Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi yóò máa wo ojú rẹ ní òdodo; nígbà tí èmi bá jí, èmi yóò ní ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí èmi bá rí àwòrán rẹ.
Já pak v spravedlnosti spatřovati budu tvář tvou; nasycen budu obrazem tvým, když procítím.

< Psalms 17 >