< Psalms 16 >

1 Miktamu ti Dafidi. Pa mí mọ́, Ọlọ́run, nítorí nínú rẹ ni ààbò mi wà.
Miktam Dawida. Strzeż mnie, o Boże, bo tobie ufam.
2 Mo sọ fún Olúwa, “Ìwọ ni Olúwa mi, lẹ́yìn rẹ èmi kò ní ìre kan.”
[Moja dusza] mówi do PANA: Ty jesteś [moim] Panem, a moja dobroć nie przynosi ci żadnej korzyści;
3 Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé, àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.
Lecz świętym, którzy są na ziemi, i szlachetnym, w których całe moje upodobanie.
4 Ìṣòro àwọn wọ̀n-ọn-nì yóò pọ̀ sí i, àní àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn. Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.
Rozmnożą się boleści tych, którzy chodzą za obcymi [bogami]. Nie złożę im ofiar z krwi i nie wymówię ich imion swoimi ustami.
5 Olúwa, ni ìpín ìní mi tí mo yàn àti ago mi, ó ti pa ohun tí í ṣe tèmi mọ́.
PAN [jest] udziałem mego dziedzictwa i kielicha; ty strzeżesz mojego losu.
6 Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára; nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.
Sznury [miernicze] wyznaczyły mi przyjemne [miejsca] i miłe jest moje dziedzictwo.
7 Èmi yóò yin Olúwa, ẹni tí ó gbà mí ní ìyànjú; ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.
Będę błogosławił PANA, który udzielił mi rady, [bo] nawet w nocy pouczają mnie moje nerki.
8 Mo ti gbé Olúwa síwájú mi ní ìgbà gbogbo. Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.
Stawiam PANA zawsze przed oczami; skoro on jest po mojej prawicy, nie zachwieję się.
9 Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀; ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,
Dlatego cieszy się moje serce i raduje się moja chwała, a moje ciało będzie spoczywać bezpiecznie.
10 nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú isà òkú, tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́. (Sheol h7585)
Nie zostawisz bowiem mojej duszy w piekle ani nie dopuścisz swemu Świętemu doznać zniszczenia. (Sheol h7585)
11 Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí; Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní iwájú rẹ, pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
Dasz mi poznać drogę życia, pełnię radości przed twoim obliczem, rozkosze po twojej prawicy na wieki.

< Psalms 16 >