< Psalms 16 >
1 Miktamu ti Dafidi. Pa mí mọ́, Ọlọ́run, nítorí nínú rẹ ni ààbò mi wà.
Dal Dávidtól. Őrizz engem, Örökkévaló, mert benned kerestem menedéket.
2 Mo sọ fún Olúwa, “Ìwọ ni Olúwa mi, lẹ́yìn rẹ èmi kò ní ìre kan.”
Mondtam az Örökkévalónak: Uram vagy, javam nincsen rajtad kívűl.
3 Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé, àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.
A szenteknek pedig, kik az országban vannak, és a dicsőknek, kikben egész kedvem van:
4 Ìṣòro àwọn wọ̀n-ọn-nì yóò pọ̀ sí i, àní àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn. Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.
Sokasodnak azoknak fájdalmai, kik más isteneket cserélnek; nem ontom véres ontóáldozataikat és nem veszem neveiket ajkaimra.
5 Olúwa, ni ìpín ìní mi tí mo yàn àti ago mi, ó ti pa ohun tí í ṣe tèmi mọ́.
Az Örökkévaló osztályomnak és serlegemnek része; te tartod az én sorsomat.
6 Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára; nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.
A mérő kötelek kellemetes helyekre estek számomra; birtokom is kedves előttem.
7 Èmi yóò yin Olúwa, ẹni tí ó gbà mí ní ìyànjú; ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.
Áldom az Örökkévalót, ki nekem tanácsot adott, éjszakákon is oktattak engem veséim.
8 Mo ti gbé Olúwa síwájú mi ní ìgbà gbogbo. Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.
Az Örökkévalót mindig magam előtt tartottam; mert jobbomon van, nem tántorgok.
9 Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀; ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,
Annak örült szívem, és vigad méltóságom; testem is bizton lakozik.
10 nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú isà òkú, tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́. (Sheol )
Mert nem hagyod lelkemet az alvilágra, nem engeded jámborodat vermet látnia. (Sheol )
11 Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí; Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní iwájú rẹ, pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
“Tudatod velem az élet ösvényét: örömök bősége van színed előtt, kellemetesség a te jobbodban mindétig!