< Psalms 16 >

1 Miktamu ti Dafidi. Pa mí mọ́, Ọlọ́run, nítorí nínú rẹ ni ààbò mi wà.
A michtam of David. Keep me, O God, for in you I take refuge.
2 Mo sọ fún Olúwa, “Ìwọ ni Olúwa mi, lẹ́yìn rẹ èmi kò ní ìre kan.”
I said to the Lord, “You are my Lord, my happiness rests in you alone.
3 Sí àwọn ènìyàn tí ó wà ní ayé, àwọn ni ológo nínú èyí tí ayọ̀ mí wà.
Those who are holy in the land, they, they alone, are the noble ones; all my delight is in them.”
4 Ìṣòro àwọn wọ̀n-ọn-nì yóò pọ̀ sí i, àní àwọn tí ń tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn. Ẹbọ ohun mímu ẹ̀jẹ̀ wọn ni èmi kì yóò ta sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá orúkọ wọn lẹ́nu mi.
Those who choose other gods find endless sorrow. In their offerings of blood I will have no part nor take their name on my lips.
5 Olúwa, ni ìpín ìní mi tí mo yàn àti ago mi, ó ti pa ohun tí í ṣe tèmi mọ́.
The Lord is my share and my portion, my fate is in your strong hands.
6 Okùn ààlà ilẹ̀ ti bọ́ sí ọ̀dọ̀ mi ní ibi dídára; nítòótọ́ mo ti ní ogún rere.
The boundary lines of my life mark out delightful country, my heritage pleases me well.
7 Èmi yóò yin Olúwa, ẹni tí ó gbà mí ní ìyànjú; ní òru, ọkàn mí ń bá mi sọ̀rọ̀.
I praise the Lord for his counsel, which so stirs my heart in the night.
8 Mo ti gbé Olúwa síwájú mi ní ìgbà gbogbo. Nítorí tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún mi, a kì yóò mì mí.
I keep the Lord always in mind: with him at my hand, I can never be moved.
9 Nítorí èyí, ọkàn mi yọ̀, ahọ́n mi pẹ̀lú ń fò fáyọ̀; ara mi pẹ̀lú yóò sinmi ní ààbò,
So my heart is glad, there is joy inside me; and in safety of body I live.
10 nítorí ìwọ kò ní fi ọ̀kan sílẹ̀ nínú isà òkú, tàbí kí ìwọ jẹ́ kí ẹni mímọ́ rẹ kí ó rí ìdíbàjẹ́. (Sheol h7585)
For you will not give me up to Sheol nor let any who love you see the pit. (Sheol h7585)
11 Ìwọ ti fi ipa ọ̀nà ìyè hàn mí; Ìwọ yóò kún mi pẹ̀lú ayọ̀ ní iwájú rẹ, pẹ̀lú ìdùnnú ayérayé ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.
You will show me the path that leads to life, to that fulness of joy which is in your presence, and the pleasures dispensed by your hand evermore.

< Psalms 16 >