< Psalms 15 >

1 Saamu ti Dafidi. Olúwa, ta ni yóò máa ṣe àtìpó nínú àgọ́ rẹ? Ta ni yóò máa gbé ní òkè mímọ́ rẹ?
Un psaume de David. Yahvé, qui habitera dans ton sanctuaire? Qui vivra sur ta sainte colline?
2 Ẹni tí ń rìn déédé tí ó sì ń sọ òtítọ́, láti inú ọkàn rẹ̀;
Celui qui marche sans reproche et fait ce qui est juste, et dit la vérité dans son cœur;
3 tí kò fi ahọ́n rẹ̀ sọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn, tí kò ṣe ibi sí aládùúgbò rẹ̀ tí kò sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí ẹnìkejì rẹ̀,
celui qui ne calomnie pas avec sa langue, ni ne fait de mal à son ami, ni ne lance d'injures contre son prochain;
4 ní ojú ẹni tí ènìyànkénìyàn di gígàn ṣùgbọ́n ó bọ̀wọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, ẹni tí ó búra sí ibi ara rẹ̀ àní tí kò sì yípadà,
aux yeux duquel un homme vil est méprisé, mais qui honore ceux qui craignent Yahvé; celui qui tient un serment même quand ça fait mal, et qui ne change pas;
5 tí ó ń yá ni lówó láìsí èlé tí kò sì gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lòdì sí aláìlẹ́ṣẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe èyí ni a kì yóò mì láéláé.
celui qui ne prête pas son argent à l'usure, ni prendre un pot-de-vin contre un innocent. Celui qui fait ces choses ne sera jamais ébranlé.

< Psalms 15 >