< Psalms 15 >

1 Saamu ti Dafidi. Olúwa, ta ni yóò máa ṣe àtìpó nínú àgọ́ rẹ? Ta ni yóò máa gbé ní òkè mímọ́ rẹ?
Žalm Davidův. Hospodine, kdo bude přebývati v stánku tvém? Kdo bydliti bude na hoře svaté tvé?
2 Ẹni tí ń rìn déédé tí ó sì ń sọ òtítọ́, láti inú ọkàn rẹ̀;
Ten, kdož chodí v upřímnosti, a činí spravedlnost, a mluví pravdu z srdce svého.
3 tí kò fi ahọ́n rẹ̀ sọ̀rọ̀ ẹni lẹ́yìn, tí kò ṣe ibi sí aládùúgbò rẹ̀ tí kò sì sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí ẹnìkejì rẹ̀,
Kdož neutrhá jazykem svým, bližnímu svému nečiní zlého, a potupy neuvodí na bližního svého.
4 ní ojú ẹni tí ènìyànkénìyàn di gígàn ṣùgbọ́n ó bọ̀wọ̀ fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, ẹni tí ó búra sí ibi ara rẹ̀ àní tí kò sì yípadà,
Ten, před jehož očima v nevážnosti jest zavržený, v poctivosti pak bojící se Hospodina; a přisáhl-li by i se škodou, však toho nemění.
5 tí ó ń yá ni lówó láìsí èlé tí kò sì gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lòdì sí aláìlẹ́ṣẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe èyí ni a kì yóò mì láéláé.
Kdož peněz svých nedává na lichvu, a daru proti nevinnému nebéře. Kdož tyto věci činí, nepohneť se na věky.

< Psalms 15 >