< Psalms 147 >

1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa, ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!
Chwalcie Pana; albowiem dobra rzecz jest, śpiewać Bogu naszemu; albowiem to wdzięczna i przystojna jest chwała.
2 Olúwa kọ́ Jerusalẹmu; Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.
Pan Jeruzalem buduje, a rozproszonego Izraela zgromadza.
3 Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.
Który uzdrawia skruszonych na sercu, a zawiązuje boleści ich.
4 Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ.
Który rachuje liczbę gwiazd, a każdą z nich imieniem jej nazywa.
5 Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára òye rẹ̀ kò sì ní òpin.
Wielki jest Pan nasz, i wielki w mocy; rozumienia jego niemasz liczby.
6 Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.
Pan pokornych podnosi; ale niepobożnych aż ku ziemi uniża.
7 Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.
Śpiewajcież Panu z chwałą; śpiewajcie Bogu naszemu na harfie;
8 Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè
Który okrywa niebiosa obłokami, a deszcz ziemi gotuje: który czyni, że rośnie trawa po górach;
9 Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.
Który daje bydłu pokarm ich, i kruczętom młodym, które wołają do niego.
10 Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin, bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin
Nie kocha się w mocy końskiej, ani się kocha w goleniach męskich.
11 Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
Kocha się Pan w tych, którzy się go boją, a którzy ufają w miłosierdziu jego.
12 Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu; yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.
Chwalże, Jeruzalemie! Pana; chwalże, Syonie! Boga twego.
13 Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára, Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ
Albowiem on umacnia zawory bram twoich, a błogosławi synów twoich w pośrodku ciebie.
14 Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.
On czyni pokój w granicach twoich, a najwyborniejszą pszenicą nasyca cię.
15 Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.
On wysyła słowo swe na ziemię; bardzo prędko bieży wyrok jego.
16 Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú
On daje śnieg jako wełnę, szron jako popiół rozsypuje.
17 Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀
Rzuca lód swój jako bryły; przed zimnem jego któż się ostoi?
18 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́ ó sì mú odò rẹ̀ sàn.
Posyła słowo swoje, i roztapia je; powienie wiatrem swym, a rozlewają wody.
19 Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli.
Oznajmuje słowo swe Jakóbowi, ustawy swe i sądy swe Izraelowi.
20 Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀ wọn ko mọ òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Nie uczynił tak żadnemu narodowi; przetoż nie poznali sądów jego. Halleluja.

< Psalms 147 >