< Psalms 147 >

1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa, ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!
Dicsérjétek az Urat! Hiszen Istenünkről énekelni jó; hiszen őt dicsérni gyönyörűséges és illendő dolog!
2 Olúwa kọ́ Jerusalẹmu; Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.
Az Úr építi Jeruzsálemet, összegyűjti Izráelnek elűzötteit;
3 Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.
Meggyógyítja a megtört szívűeket, és bekötözi sebeiket.
4 Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ.
Elrendeli a csillagok számát, és mindnyájokat nevéről nevezi.
5 Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára òye rẹ̀ kò sì ní òpin.
Nagy a mi Urunk és igen hatalmas, s bölcseségének nincsen határa.
6 Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.
Megtartja az Úr a nyomorultakat; a gonoszokat földig megalázza.
7 Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.
Énekeljetek az Úrnak hálaadással, pengessetek hárfát a mi Istenünknek!
8 Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè
A ki beborítja az eget felhővel, esőt készít a föld számára, és füvet sarjaszt a hegyeken;
9 Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.
A ki megadja táplálékát a baromnak, a holló-fiaknak, a melyek kárognak.
10 Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin, bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin
Nem paripák erejében telik kedve, nem is a férfi lábszáraiban gyönyörködik;
11 Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
Az őt félőkben gyönyörködik az Úr, a kik kegyelmében reménykednek.
12 Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu; yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.
Dicsőitsd Jeruzsálem az Urat! Dicsérd, oh Sion, a te Istenedet!
13 Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára, Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ
Mert erősekké teszi kapuid zárait, s megáldja benned a te fiaidat.
14 Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.
Békességet ád határaidnak, megelégít téged a legjobb búzával.
15 Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.
Leküldi parancsolatát a földre, nagy hirtelen lefut az ő rendelete!
16 Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú
Olyan havat ád, mint a gyapjú, és szórja a deret, mint a port.
17 Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀
Darabokban szórja le jegét: ki állhatna meg az ő fagya előtt?
18 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́ ó sì mú odò rẹ̀ sàn.
Kibocsátja szavát s szétolvasztja őket; megindítja szelét s vizek folydogálnak.
19 Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli.
Közli igéit Jákóbbal, törvényeit s végzéseit Izráellel.
20 Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀ wọn ko mọ òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Nem tesz így egyetlen néppel sem; végzéseit sem tudatja velök. Dicsérjétek az Urat!

< Psalms 147 >