< Psalms 147 >
1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa, ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!
Louez le Seigneur, car il est bon; qu’on célèbre notre Dieu, car il est aimable: à lui conviennent les louanges.
2 Olúwa kọ́ Jerusalẹmu; Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.
L’Eternel rebâtira Jérusalem, il y rassemblera les débris dispersés d’Israël.
3 Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.
C’Est lui qui guérit les cœurs brisés et panse leurs douloureuses blessures.
4 Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ.
Il détermine le nombre des étoiles, à elles toutes il attribue des noms.
5 Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára òye rẹ̀ kò sì ní òpin.
Grand est notre Maître et tout-puissant, sa sagesse est sans limites.
6 Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.
L’Eternel soutient les humbles, il abaisse jusqu’à terre les méchants.
7 Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.
Entonnez des actions de grâce en l’honneur de l’Eternel. Célébrez notre Dieu au son de la harpe.
8 Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè
C’Est lui qui couvre le ciel de nuages, prépare la pluie pour la terre, fait pousser l’herbe sur les montagnes.
9 Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.
Il donne leur pâture aux bêtes, aux petits des corbeaux qui la réclament.
10 Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin, bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin
Il ne prend point plaisir à la vigueur du coursier, il ne tient pas à l’agilité de l’homme;
11 Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
ce qu’il aime, l’Eternel, ce sont ses adorateurs, ceux qui ont foi en sa bonté.
12 Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu; yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.
Célèbre, ô Jérusalem, l’Eternel, glorifie ton Dieu, ô Sion!
13 Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára, Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ
Car il a consolidé les barres de tes portes, il a béni tes fils dans ton enceinte,
14 Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.
C’Est lui qui a fait régner la paix sur ton sol, qui te rassasie de la moelle du froment.
15 Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.
Il envoie ses ordres sur la terre, sa parole vole avec une extrême rapidité.
16 Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú
Il répand la neige comme des flocons de laine, sème le givre comme de la cendre.
17 Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀
Il lance des glaçons par morceaux: qui peut tenir devant ses frimas?
18 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́ ó sì mú odò rẹ̀ sàn.
Il émet un ordre, et le dégel s’opère; il fait souffler le vent: les eaux reprennent leur cours.
19 Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli.
Il a révélé ses paroles à Jacob, ses statuts et ses lois de justice à Israël.
20 Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀ wọn ko mọ òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
Il n’a fait cela pour aucun des autres peuples; aussi ses lois leur demeurent-elles inconnues. Alléluia!