< Psalms 146 >

1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Fi ìyìn fún Olúwa, ìwọ ọkàn mi.
Alleluja. Chwal, duszo moja, PANA.
2 Èmi yóò yin Olúwa ní gbogbo ayé mi, èmi yóò kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, níwọ̀n ìgbà tí mo bá wà láààyè.
Będę chwalić PANA, póki żyję; będę śpiewał memu Bogu, póki będę istniał.
3 Ẹ má ṣe ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú àwọn ọmọ-aládé, àní, ọmọ ènìyàn, lọ́wọ́ ẹni tí kò sí ìrànlọ́wọ́.
Nie pokładajcie ufności we władcach [ani w żadnym] synu ludzkim, u którego nie ma wybawienia.
4 Ẹ̀mí rẹ jáde lọ, ó padà sí erùpẹ̀, ní ọjọ́ náà gan, èrò wọn yóò di òfo.
Opuszcza go duch i wraca do swojej ziemi; w tymże dniu zginą [wszystkie] jego myśli.
5 Ìbùkún ni fún ẹni tí Ọlọ́run Jakọbu ń ṣe ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ tí ìrètí rẹ̀ wà nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Błogosławiony ten, kogo pomocą jest Bóg Jakuba, kto nadzieję pokłada w PANU, jego Bogu;
6 Ẹni tí ó dá ọ̀run àti ayé, òkun àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú wọn, ẹni tí ó pa òtítọ́ mọ́ títí ayé.
Który uczynił niebo i ziemię, morze i wszystko, co w nich [jest]; który dochowuje prawdy na wieki;
7 Ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ àwọn tí a ni lára, tí ó fi oúnjẹ fún àwọn tí ebi ń pa, Olúwa, tú àwọn oǹdè sílẹ̀,
Który oddaje sprawiedliwość pokrzywdzonym [i] daje chleb głodnym; PAN uwalnia więźniów.
8 Olúwa mú àwọn afọ́jú ríran, Olúwa, gbé àwọn tí a rẹ̀ sílẹ̀ ga, Olúwa fẹ́ràn àwọn olódodo.
PAN otwiera [oczy] ślepych; PAN podnosi przygnębionych; PAN miłuje sprawiedliwych.
9 Olúwa ń dá ààbò bo àwọn àlejò ó sì ń dá àwọn aláìní baba àti opó sí ṣùgbọ́n ó ba ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú jẹ́.
PAN strzeże przychodniów, wspomaga sierotę i wdowę, ale krzyżuje drogę niegodziwych.
10 Olúwa jẹ ọba títí láé; Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni, àti fún gbogbo ìran. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.
PAN będzie królował na wieki, twój Bóg, o Syjonie, z pokolenia na pokolenie. Alleluja.

< Psalms 146 >