< Psalms 145 >
1 Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
Un salmo of David. Un canto de alabanza. ¡Te glorificaré, mi Dios y Rey! ¡Por siempre y para siempre alabaré quien eres!
2 Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
Te alabaré cada día. ¡Alabaré tu nombre por siempre y para siempre!
3 Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
¡El Señor es grande y es digno de suprema alabanza! ¡Su grandeza no se puede medir!
4 Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
¡Que todas las generaciones cuenten tus obras y compartan las historias de tus asombrosos milagros!
5 Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Ellos hablarán de tu majestad, de tu glorioso esplendor, y yo meditaré en las maravillas que has hecho.
6 Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
Ellos hablarán del poder de tus actos, y yo diré cuán maravilloso eres.
7 Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
Ellos le contarán a todos de tu renombre por tu gran bondad y con alegría celebrarán que siempre haces lo recto.
8 Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
El Señor es misericordioso, lento para enojarse, y lleno de amor inagotable.
9 Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
El Señor es bueno con todos, y muestra misericordia hacia todas sus criaturas.
10 Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
Todos los seres creados te agradecerán, oh Señor, y te alabarán todos los que fielmente te siguen.
11 Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
Alabarán la gloria de tu reino, y hablarán de tu poder.
12 kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
Contarán a los pueblos sobre tus maravillosos milagros, y el glorioso esplendor de tu reino.
13 Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
Tu reino no tiene fin, y tu gobierno se extiende por todas las generaciones. Las promesas del señor son fieles y él es misericordioso en todos sus actos.
14 Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
El Señor ayuda a los caídos y levanta a los que están abatidos.
15 Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
Todos los ojos están puestos en ti, llenos de esperanza; y tú les das alimentos a quienes lo necesitan a su tiempo.
16 Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
Tú das con generosidad y satisfaces las necesidades de todos los seres vivientes.
17 Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
El Señor hace lo recto en todas las cosas. Su fidelidad está en cada uno de sus actos.
18 Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
El Señor está cerca de los que piden su ayuda, de los que le piden de corazón.
19 Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
Él satisface las necesidades de quienes lo siguen. Escucha su clamor de ayuda y los salva.
20 Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
El Señor cuida de quienes lo aman, pero destruirá a los malvados.
21 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.
Alabaré al Señor, y que todo el mundo honre su nombre, por siempre y para siempre.