< Psalms 145 >

1 Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
Cântico de Davi: Eu te exaltarei, meu Deus [e] Rei; e bendirei teu nome para todo o sempre.
2 Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
Todo dia eu te bendirei, e louvarei teu nome para todo o sempre.
3 Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
O SENHOR é grande e muito louvável; sua grandeza é incompreensível.
4 Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
Geração após geração louvará tuas obras, e anunciarão tuas proezas.
5 Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Eu falarei da honra gloriosa de tua majestade, e de teus feitos maravilhosos.
6 Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
E falarão do poder de teus assombrosos feitos; e eu contarei tua grandeza.
7 Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
Declararão a lembrança de tua grande bondade; e anunciarão tua justiça alegremente.
8 Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
Piedoso e misericordioso é o SENHOR; ele demora para se irar, e tem grande bondade.
9 Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
O SENHOR é bom para com todos; e suas misericórdias [estão] sobre todas as obras que ele fez.
10 Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
Todas as tuas obras louvarão a ti, SENHOR; e teus santos te bendirão.
11 Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
Contarão a glória de teu reino, e falarão de teu poder.
12 kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
Para anunciarem aos filhos dos homens suas proezas, e a honra gloriosa de seu reino.
13 Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
Teu reino é um reino eterno, e teu domínio [dura] geração após geração.
14 Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
O SENHOR segura todos os que caem, e levanta todos os abatidos.
15 Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
Os olhos de todos esperam por ti, e tu lhes dás seu alimento ao seu tempo.
16 Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
Tu abres tua mão, e sacias o desejo de todo ser vivo.
17 Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
O SENHOR [é] justo em todos os seus caminhos, e bondoso em todas as suas obras.
18 Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
O SENHOR está perto de todos os que o chamam; de todos os que clamam a ele sinceramente.
19 Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
Ele faz a vontade dos que o temem; e ouve o clamor deles, e os salva.
20 Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
O SENHOR protege a todos os que o amam; porém destrói a todos os perversos.
21 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.
Minha boca anunciará louvores ao SENHOR; e todo [ser feito de] carne louvará seu santo nome para todo o sempre.

< Psalms 145 >