< Psalms 145 >

1 Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
Eu te exaltarei, ó Deus, rei meu, e bendirei o teu nome pelo século do século e para sempre.
2 Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
Cada dia te bendirei, e louvarei o teu nome pelo século do século e para sempre.
3 Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
Grande é o Senhor, e muito digno de louvor, e a sua grandeza inexcrutável.
4 Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
Uma geração louvará as tuas obras à outra geração, e anunciarão as tuas proezas.
5 Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Falarei da magnificência gloriosa da tua magestade e das tuas obras maravilhosas.
6 Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
E se falará da força dos teus feitos terríveis; e contarei a tua grandeza.
7 Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
Proferirão abundantemente a memória da tua grande bondade, e cantarão a tua justiça.
8 Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
Piedoso e benigno é o Senhor, sofredor e de grande misericórdia.
9 Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
O Senhor é bom para todos, e as suas misericórdias são sobre todas as suas obras.
10 Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
Todas as tuas obras te louvarão, ó Senhor, e os teus santos te bendirão.
11 Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
Falarão da glória do teu reino, e relatarão o teu poder,
12 kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
Para fazer saber aos filhos dos homens as tuas proezas e a glória da magnificência do teu reino.
13 Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
O teu reino é um reino eterno; o teu domínio dura em todas as gerações.
14 Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
O Senhor sustenta a todos os que caem, e levanta a todos os abatidos.
15 Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
Os olhos de todos esperam em ti, e lhes dás o seu mantimento a seu tempo.
16 Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
Abres a tua mão, e fartas os desejos de todos os viventes.
17 Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
Justo é o Senhor em todos os seus caminhos, e santo em todas as suas obras.
18 Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
Perto está o Senhor de todos os que o invocam, de todos os que o invocam em verdade.
19 Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
Ele cumprirá o desejo dos que o temem; ouvirá o seu clamor, e os salvará.
20 Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
O Senhor guarda a todos os que o amam; porém todos os ímpios serão destruídos.
21 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.
A minha boca falará o louvor do Senhor, e toda a carne louvará o seu santo nome pelo século do século e para sempre.

< Psalms 145 >