< Psalms 145 >

1 Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
Pieśń pochwalna Dawida. Będę cię wywyższać, Boże mój, królu [mój], i będę błogosławić twe imię na wieki wieków.
2 Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
Każdego dnia będę cię błogosławić i chwalić twoje imię na wieki wieków.
3 Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
Wielki jest PAN i godzien wielkiej chwały, a jego wielkość jest niezbadana.
4 Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
Pokolenie pokoleniu będzie wychwalać twoje dzieła i opowiadać o twoich potężnych czynach.
5 Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Będę wysławiać wspaniałość chwały twojego majestatu i twoje cudowne dzieła.
6 Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
I będą mówić o mocy twoich straszliwych [czynów], a [ja] będę opowiadać twoją wielkość.
7 Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
Będą wysławiać pamięć twojej wielkiej dobroci i śpiewać o twojej sprawiedliwości.
8 Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
Łaskawy jest PAN i litościwy, nieskory do gniewu i bardzo miłosierny.
9 Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
Dobry jest PAN dla wszystkich, a jego miłosierdzie nad wszystkimi jego dziełami.
10 Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
Twoje dzieła będą cię wysławiać, PANIE, a twoi święci będą ci błogosławić.
11 Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
Będą opowiadać o chwale twego królestwa i mówić o twojej potędze;
12 kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
Aby oznajmić synom ludzkim jego potężne czyny [i] wspaniałą chwałę jego królestwa.
13 Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
Twoje królestwo [jest] królestwem wiecznym, a twoje panowanie [trwa] przez wszystkie pokolenia.
14 Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
PAN podtrzymuje wszystkich, którzy upadają, i podnosi wszystkich przygnębionych.
15 Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
Oczy wszystkich oczekują ciebie, a ty im dajesz pokarm we właściwym czasie.
16 Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
Otwierasz swoją rękę i nasycasz do woli wszystko, co żyje.
17 Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
Sprawiedliwy [jest] PAN we wszystkich swoich drogach i miłosierny we wszystkich swoich dziełach.
18 Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
Bliski [jest] PAN wszystkim, którzy go wzywają; wszystkim, którzy go wzywają w prawdzie.
19 Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
Spełni pragnienia tych, którzy się go boją; usłyszy ich wołanie i wybawi ich.
20 Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
PAN strzeże wszystkich, którzy go miłują; a wytraci wszystkich niegodziwych.
21 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.
Moje usta będą głosić chwałę PANA i niech wszelkie ciało błogosławi jego święte imię na wieki wieków.

< Psalms 145 >