< Psalms 145 >

1 Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
Jeg vil ophøje dig, min Gud, du som er Kongen! og love dit Navn evindelig og altid.
2 Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
Hver Dag vil jeg love dig og prise dit Navn evindelig og altid.
3 Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
Herren er stor og saare priselig, og hans Magt er uransagelig.
4 Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
En Slægt skal berømme for den anden dine Gerninger, og de skulle forkynde din Vælde.
5 Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Jeg vil betænke din Majestæts herlige Ære og dine underfalde Gerninger.
6 Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
Og der skal tales om dine forfærdelige Gerningers Vælde, og jeg vil fortælle om din Magt.
7 Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
De skulle udbrede din store Godheds Ihukommelse og synge med Fryd om din Retfærdighed.
8 Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
Herren er naadig og barmhjertig, langmodig og af stor Miskundhed.
9 Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
Herren er god imod alle, og hans Barmhjertighed er over alle hans Gerninger.
10 Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
Dig, Herre! skulle alle dine Gerninger prise og dine hellige love dig.
11 Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
De skulle forkynde dit Riges Ære, tale om din Vælde,
12 kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
for at kundgøre for Menneskens Børn hans Vælde og hans Riges herlige Ære.
13 Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
Dit Rige er et Rige i al Evighed, og dit Herredømme varer fra Slægt til Slægt.
14 Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
Herren opholder alle dem, som falde, og oprejser alle de nedbøjede.
15 Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
Alles Øjne vogte paa dig, og du giver dem deres Spise i sin Tid.
16 Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
Du oplader din Haand og mætter alt det, som lever, med Velbehagelighed.
17 Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
Herren er retfærdig i alle sine Veje og miskundelig i alle sine Gerninger.
18 Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
Herren er nær hos alle, som kalde paa ham, hos alle, som kalde paa ham i Sandhed.
19 Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
Han gør efter deres Velbehagelighed, som ham frygte, og han hører deres Skrig og frelser dem.
20 Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
Herren bevarer alle dem, som elske ham, men han ødelægger alle de ugudelige.
21 Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.
Min Mund skal udtale Herrens Lov, og alt Kød skal love hans hellige Navn evindelig og altid.

< Psalms 145 >