< Psalms 144 >

1 Ti Dafidi. Ìyìn sí Olúwa àpáta mi, ẹni tí ó kọ́ ọwọ́ mi fún ogun, àti ìka mi fún ìjà.
Dawut yazghan küy: — Qollirimgha jeng qilishni, Barmaqlirimgha urushni ögitidighan, Méning Qoram Téshim Perwerdigargha teshekkür-medhiye qayturulsun!
2 Òun ni Ọlọ́run ìfẹ́ mi àti odi alágbára mi, ibi gíga mi àti olùgbàlà mi, asà mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó tẹrí àwọn ènìyàn ba lábẹ́ mi.
Méning özgermes shepqitim we méning qorghinim, Méning égiz munarim we nijatkarim, Méning qalqinim we tayan’ghinim, men Uningdin himaye tapimen; U Öz xelqimni qol astimda boysundurghuchidur!
3 Olúwa, kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣàníyàn fún un, tàbí ọmọ ènìyàn tí ìwọ fi ń ronú nípa rẹ̀?
I Perwerdigar, Sen uningdin xewer alidikensen, adem dégen zadi néme? Uning toghruluq oylaydikensen, insan balisi dégen néme?
4 Ènìyàn rí bí èmi; ọjọ́ rẹ̀ rí bí òjìji tí ń kọjá lọ.
Adem bolsa bir nepesturla, xalas; Uning künliri ötüp kétiwatqan bir kölenggidur, xalas.
5 Tẹ ọ̀run rẹ ba, Olúwa, kí o sì sọ̀kalẹ̀; tọ́ àwọn òkè ńlá wọn yóò sí rú èéfín.
I Perwerdigar, asmanlarni égildürüp chüshkeysen; Taghlargha tégip ulardin is-tütek chiqarghaysen;
6 Rán mọ̀nàmọ́ná kí ó sì fọ́n àwọn ọ̀tá ká; ta ọfà rẹ kí ó sì dà wọ́n rú.
Chaqmaqlarni chaqquzup ularni tarqitiwetkeysen; Oqliringni étip ularni qiyqas-süren’ge salghaysen;
7 Na ọwọ́ rẹ sílẹ̀ láti ibi gíga; gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu kúrò nínú omi ńlá: kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì.
Yuqiridin qolliringni uzitip, Méni azad qilghaysen; Méni ulugh sulardin, Yaqa yurttikilerning changgilidin chiqarghaysen.
8 Ẹnu ẹni tí ó kún fún èké ẹni tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jẹ́ ìrẹ́jẹ.
Ularning aghzi quruq gep sözleydu, Ong qoli aldamchi qoldur.
9 Èmi yóò kọ orin tuntun sí ọ Ọlọ́run; lára ohun èlò orin olókùn mẹ́wàá èmi yóò kọ orin sí ọ.
I Xuda, men Sanga atap yéngi naxsha éytimen; Ontargha tengkesh bolup Sanga küylerni éytimen.
10 Òun ni ó fi ìgbàlà fún àwọn ọba, ẹni tí ó gba Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ idà ìpanilára. Lọ́wọ́ pípanirun.
Sen padishahlargha nijatliq-ghelibe béghishlaysen; Qulung Dawutni ejellik qilichtin qutuldurisen.
11 Gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì tí ẹnu wọn kún fún èké, tí ọwọ́ ọ̀tún wọn jẹ́ ọwọ́ ọ̀tún èké.
Méni qutuldurghaysen, yat yurttikilerning qolidin azad qilghaysen; Ularning aghzi quruq gep sözleydu, Ong qoli aldamchi qoldur.
12 Kí àwọn ọmọkùnrin wa kí ó dàbí igi gbígbìn tí ó dàgbà ni ìgbà èwe wọn, àti ọmọbìnrin wa yóò dàbí òpó ilé tí a ṣe ọ̀nà sí bí àfarawé ààfin.
Shundaq qilip oghullirimiz yashliqida puxta yétilgen köchetlerge oxshaydu, Qizlirimiz ordiche neqishlen’gen tüwrüklerdek bolidu;
13 Àká wa yóò kún pẹ̀lú gbogbo onírúurú oúnjẹ àgùntàn wa yóò pọ̀ si ní ẹgbẹ̀rún, ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní oko wa:
Ashliq ambarlirimiz toldurulup, Türlük-türlük ozuqlar bilen teminleydighan, Qoylirimiz otlaqlirimizda minglap, tümenlep qozilaydighan;
14 àwọn màlúù wa yóò ru ẹrù wúwo kí ó má sí ìkọlù, kí ó má sí ìkólọ sí ìgbèkùn, kí ó má sí i igbe ìpọ́njú ní ìgboro wa.
Kalilirimiz boghaz bolidighan; Héchkim bésip kirmeydighan, héchkim [jengge] chiqmaydighan; Kochilirimizda héch jédel-ghowgha bolmaydighan;
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà tí ó wà ní irú ipò bẹ́ẹ̀, ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà, tí ẹni tí Ọlọ́run Olúwa ń ṣe.
Ehwali shundaq bolghan xelq némidégen bextliktur! Xudasi Perwerdigar bolghan xelq bextliktur!

< Psalms 144 >