< Psalms 144 >
1 Ti Dafidi. Ìyìn sí Olúwa àpáta mi, ẹni tí ó kọ́ ọwọ́ mi fún ogun, àti ìka mi fún ìjà.
Pieśń Dawida. Błogosławiony PAN, moja skała, który zaprawia moje ręce do walki, a moje palce do wojny.
2 Òun ni Ọlọ́run ìfẹ́ mi àti odi alágbára mi, ibi gíga mi àti olùgbàlà mi, asà mi, ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé, ẹni tí ó tẹrí àwọn ènìyàn ba lábẹ́ mi.
Moje miłosierdzie i moja twierdza, moja warownia, mój wybawiciel i moja tarcza; ten, któremu ufam, on mi poddaje mój lud.
3 Olúwa, kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣàníyàn fún un, tàbí ọmọ ènìyàn tí ìwọ fi ń ronú nípa rẹ̀?
PANIE, czym jest człowiek, że zwracasz na niego uwagę? [Albo] syn człowieczy, że go poważasz?
4 Ènìyàn rí bí èmi; ọjọ́ rẹ̀ rí bí òjìji tí ń kọjá lọ.
Człowiek jest podobny do marności; jego dni jak cień, który przemija.
5 Tẹ ọ̀run rẹ ba, Olúwa, kí o sì sọ̀kalẹ̀; tọ́ àwọn òkè ńlá wọn yóò sí rú èéfín.
PANIE, nachyl twoich niebios i zstąp; dotknij gór, a będą dymić.
6 Rán mọ̀nàmọ́ná kí ó sì fọ́n àwọn ọ̀tá ká; ta ọfà rẹ kí ó sì dà wọ́n rú.
Zabłyśnij błyskawicą i rozprosz ich; wypuść swoje strzały i poraź ich.
7 Na ọwọ́ rẹ sílẹ̀ láti ibi gíga; gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu kúrò nínú omi ńlá: kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì.
Wyciągnij swą rękę z wysokości; wybaw mnie i ocal z wielkich wód, z rąk cudzoziemców;
8 Ẹnu ẹni tí ó kún fún èké ẹni tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jẹ́ ìrẹ́jẹ.
Których usta mówią kłamstwo, a ich prawica jest prawicą fałszywą.
9 Èmi yóò kọ orin tuntun sí ọ Ọlọ́run; lára ohun èlò orin olókùn mẹ́wàá èmi yóò kọ orin sí ọ.
Boże, zaśpiewam tobie nową pieśń; będę ci śpiewał przy [dźwiękach] lutni i harfy o dziesięciu strunach.
10 Òun ni ó fi ìgbàlà fún àwọn ọba, ẹni tí ó gba Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ idà ìpanilára. Lọ́wọ́ pípanirun.
[Ty] dajesz królom zwycięstwo, [a] Dawida, swego sługę, wybawiasz od srogiego miecza.
11 Gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì tí ẹnu wọn kún fún èké, tí ọwọ́ ọ̀tún wọn jẹ́ ọwọ́ ọ̀tún èké.
Wybaw mnie i ocal z rąk cudzoziemców, których usta mówią kłamstwo, a ich prawica jest prawicą fałszywą;
12 Kí àwọn ọmọkùnrin wa kí ó dàbí igi gbígbìn tí ó dàgbà ni ìgbà èwe wọn, àti ọmọbìnrin wa yóò dàbí òpó ilé tí a ṣe ọ̀nà sí bí àfarawé ààfin.
Aby nasi synowie byli jak szczepy wyrosłe w swojej młodości, [a] nasze córki jak kamienie węgielne, wyrzeźbione na wzór pałacu;
13 Àká wa yóò kún pẹ̀lú gbogbo onírúurú oúnjẹ àgùntàn wa yóò pọ̀ si ní ẹgbẹ̀rún, ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní oko wa:
[Aby] nasze spichlerze były pełne, obficie zaopatrzone we wszystko, nasze stada rodziły tysiące i dziesięć tysięcy w naszych zagrodach;
14 àwọn màlúù wa yóò ru ẹrù wúwo kí ó má sí ìkọlù, kí ó má sí ìkólọ sí ìgbèkùn, kí ó má sí i igbe ìpọ́njú ní ìgboro wa.
[Aby] nasze woły były tłuste, żeby nie było włamań ani ucieczek, ani narzekania na naszych ulicach.
15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà tí ó wà ní irú ipò bẹ́ẹ̀, ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà, tí ẹni tí Ọlọ́run Olúwa ń ṣe.
Błogosławiony lud, któremu się tak dzieje. Błogosławiony lud, którego Bogiem jest PAN.