< Psalms 143 >

1 Saamu ti Dafidi. Olúwa gbọ́ àdúrà mi, fetísí igbe mi fún àánú; nínú òtítọ́ àti òdodo rẹ, wá fún ìrànlọ́wọ́ mi.
Um salmo de David. Ouça minha oração, Yahweh. Ouça minhas petições. Em sua fidelidade e retidão, alivie-me.
2 Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìdájọ́, nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wà láààyè tí ó ṣe òdodo níwájú rẹ.
Não entre em julgamento com seu servo, pois na sua visão, nenhum homem que vive é justo.
3 Ọ̀tá ń lépa mi, ó fún mi pamọ́ ilẹ̀; ó mú mi gbé nínú òkùnkùn bí àwọn tí ó ti kú ti pẹ́.
Pois o inimigo persegue minha alma. Ele deu cabo da minha vida. Ele me fez viver em lugares escuros, como aqueles que já morreram há muito tempo.
4 Nítorí náà ẹ̀mí mi ṣe rẹ̀wẹ̀sì nínú mi; ọkàn mi nínú mi ṣì pòruurù.
Therefore meu espírito está dominado dentro de mim. Meu coração dentro de mim está desolado.
5 Èmi rántí ọjọ́ tí ó ti pẹ́; èmi ń ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ mo sì ṣe àkíyèsí ohun tí ọwọ́ rẹ ti ṣe.
Lembro-me dos dias de antigamente. Medito em todos os seus atos. Contemplo o trabalho de suas mãos.
6 Èmi na ọwọ́ mi jáde sí ọ: òǹgbẹ rẹ gbẹ ọkàn mi bí i ìyàngbẹ ilẹ̀. (Sela)
Eu estendo minhas mãos para você. Minha alma tem sede por você, como uma terra ressequida. (Selah)
7 Dá mi lóhùn kánkán, Olúwa; ó rẹ ẹ̀mí mi tán. Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lára mi kí èmi má ba à dàbí àwọn tí ó lọ sínú ihò.
Hurry para me responder, Yahweh. Meu espírito falha. Não esconda seu rosto de mim, para que eu não me torne como aqueles que descem para o poço.
8 Mú mi gbọ́ ìṣeun ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀: nítorí ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé. Fi ọ̀nà tí èmi i bá rìn hàn mí, nítorí èmi gbé ọkàn mi sókè sí ọ.
Cause me para ouvir sua amorosa gentileza pela manhã, pois eu confio em você. Porque eu sei como devo andar, pois eu levanto minha alma para você.
9 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, Olúwa, nítorí èmi fi ara mi pamọ́ sínú rẹ.
Entregue-me, Yahweh, de meus inimigos. Eu fujo para você para me esconder.
10 Kọ́ mi láti ṣe ìfẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run mi jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ dídára darí mi sí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú.
Ensine-me a fazer sua vontade, pois você é meu Deus. Seu Espírito é bom. Conduza-me na terra da retidão.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, sọ mi di ààyè; nínú òdodo rẹ, mú ọkàn mi jáde nínú wàhálà.
Reanime-me, Yahweh, pelo seu nome. Em sua retidão, tire minha alma de apuros.
12 Nínú ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà, ké àwọn ọ̀tá mi kúrò, run gbogbo àwọn tí ń ni ọkàn mi lára, nítorí pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ.
Em sua amorosa gentileza, corte meus inimigos, e destruir todos aqueles que afligem minha alma, pois eu sou seu servo.

< Psalms 143 >