< Psalms 143 >

1 Saamu ti Dafidi. Olúwa gbọ́ àdúrà mi, fetísí igbe mi fún àánú; nínú òtítọ́ àti òdodo rẹ, wá fún ìrànlọ́wọ́ mi.
Ó Senhor, ouve a minha oração, inclina os ouvidos às minhas suplicas: escuta-me segundo a tua verdade, e segundo a tua justiça,
2 Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìdájọ́, nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wà láààyè tí ó ṣe òdodo níwájú rẹ.
E não entres em juízo com o teu servo, porque à tua vista não se achará justo nenhum vivente.
3 Ọ̀tá ń lépa mi, ó fún mi pamọ́ ilẹ̀; ó mú mi gbé nínú òkùnkùn bí àwọn tí ó ti kú ti pẹ́.
Pois o inimigo perseguiu a minha alma; atropelou-me até ao chão; fêz-me habitar na escuridão, como aqueles que morreram há muito.
4 Nítorí náà ẹ̀mí mi ṣe rẹ̀wẹ̀sì nínú mi; ọkàn mi nínú mi ṣì pòruurù.
Pelo que o meu espírito se angústia em mim; e o meu coração em mim está desolado.
5 Èmi rántí ọjọ́ tí ó ti pẹ́; èmi ń ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ mo sì ṣe àkíyèsí ohun tí ọwọ́ rẹ ti ṣe.
Lembro-me dos dias antigos; considero todos os teus feitos; medito na obra das tuas mãos.
6 Èmi na ọwọ́ mi jáde sí ọ: òǹgbẹ rẹ gbẹ ọkàn mi bí i ìyàngbẹ ilẹ̀. (Sela)
Estendo para ti as minhas mãos; a minha alma tem sede de ti, como terra sedenta (Selah)
7 Dá mi lóhùn kánkán, Olúwa; ó rẹ ẹ̀mí mi tán. Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lára mi kí èmi má ba à dàbí àwọn tí ó lọ sínú ihò.
Ouve-me depressa, ó Senhor; o meu espírito desmaia; não escondas de mim a tua face, para que não seja semelhante aos que descem à cova.
8 Mú mi gbọ́ ìṣeun ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀: nítorí ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé. Fi ọ̀nà tí èmi i bá rìn hàn mí, nítorí èmi gbé ọkàn mi sókè sí ọ.
Faze-me ouvir a tua benignidade pela manhã, pois em ti confio; faze-me saber o caminho que devo seguir, porque a ti levanto a minha alma.
9 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, Olúwa, nítorí èmi fi ara mi pamọ́ sínú rẹ.
Livra-me, ó Senhor, dos meus inimigos; fujo para ti, para me esconder.
10 Kọ́ mi láti ṣe ìfẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run mi jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ dídára darí mi sí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú.
Ensina-me a fazer a tua vontade, pois és o meu Deus: o teu espírito é bom; guia-me por terra plana.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, sọ mi di ààyè; nínú òdodo rẹ, mú ọkàn mi jáde nínú wàhálà.
Vivifica-me, ó Senhor, por amor do teu nome; por amor da tua justiça, tira a minha alma da angústia.
12 Nínú ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà, ké àwọn ọ̀tá mi kúrò, run gbogbo àwọn tí ń ni ọkàn mi lára, nítorí pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ.
E por tua misericórdia desarreiga os meus inimigos, e destrói a todos os que angustiam a minha alma: pois sou teu servo.

< Psalms 143 >