< Psalms 143 >

1 Saamu ti Dafidi. Olúwa gbọ́ àdúrà mi, fetísí igbe mi fún àánú; nínú òtítọ́ àti òdodo rẹ, wá fún ìrànlọ́wọ́ mi.
Žalm Davidův. Hospodine, slyš modlitbu mou, pozoruj pokorné prosby mé; pro pravdu svou vyslyš mne, i pro spravedlnost svou.
2 Má ṣe mú ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìdájọ́, nítorí kò sí ẹnìkan tí ó wà láààyè tí ó ṣe òdodo níwájú rẹ.
A nevcházej v soud s služebníkem svým, neboť by nebyl spravedliv před tebou nižádný živý.
3 Ọ̀tá ń lépa mi, ó fún mi pamọ́ ilẹ̀; ó mú mi gbé nínú òkùnkùn bí àwọn tí ó ti kú ti pẹ́.
Nebo stihá nepřítel duši mou, potírá až k zemi život můj; na to mne přivodí, abych bydlil v mrákotě, jako ti, kteříž již dávno zemřeli,
4 Nítorí náà ẹ̀mí mi ṣe rẹ̀wẹ̀sì nínú mi; ọkàn mi nínú mi ṣì pòruurù.
Tak že se svírá úzkostmi duch můj ve mně, u vnitřnosti mé hyne srdce mé.
5 Èmi rántí ọjọ́ tí ó ti pẹ́; èmi ń ṣe àṣàrò lórí gbogbo iṣẹ́ rẹ mo sì ṣe àkíyèsí ohun tí ọwọ́ rẹ ti ṣe.
Rozpomínaje se na dny předešlé, a rozvažuje všecky skutky tvé, a dílo rukou tvých rozjímaje,
6 Èmi na ọwọ́ mi jáde sí ọ: òǹgbẹ rẹ gbẹ ọkàn mi bí i ìyàngbẹ ilẹ̀. (Sela)
Vztahuji ruce své k tobě, duše má jako země vyprahlá žádá tebe. (Sélah)
7 Dá mi lóhùn kánkán, Olúwa; ó rẹ ẹ̀mí mi tán. Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ kúrò lára mi kí èmi má ba à dàbí àwọn tí ó lọ sínú ihò.
Pospěšiž a vyslyš mne, Hospodine, hyne duch můj; neukrývejž tváři své přede mnou, neboť jsem podobný těm, kteříž sstupují do hrobu.
8 Mú mi gbọ́ ìṣeun ìfẹ́ rẹ ní òwúrọ̀: nítorí ìwọ ni mo gbẹ́kẹ̀lé. Fi ọ̀nà tí èmi i bá rìn hàn mí, nítorí èmi gbé ọkàn mi sókè sí ọ.
Učiň to, ať v jitře slyším milosrdenství tvé, neboť v tobě naději mám; oznam mi cestu, po kteréž bych choditi měl, neboť k tobě pozdvihuji duše své.
9 Gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi, Olúwa, nítorí èmi fi ara mi pamọ́ sínú rẹ.
Vytrhni mne z nepřátel mých, Hospodine, u tebeť se skrývám.
10 Kọ́ mi láti ṣe ìfẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run mi jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ dídára darí mi sí ilẹ̀ tí ó tẹ́jú.
Nauč mne činiti vůle tvé, nebo ty jsi Bůh můj; duch tvůj dobrý vediž mne jako po rovné zemi.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, sọ mi di ààyè; nínú òdodo rẹ, mú ọkàn mi jáde nínú wàhálà.
Pro jméno své, Hospodine, obživ mne, pro spravedlnost svou vyveď z úzkosti duši mou.
12 Nínú ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà, ké àwọn ọ̀tá mi kúrò, run gbogbo àwọn tí ń ni ọkàn mi lára, nítorí pé èmi ni ìránṣẹ́ rẹ.
A pro milosrdenství své vypleň nepřátely mé, a vyhlaď všecky, kteříž trápí duši mou; nebo já jsem služebník tvůj.

< Psalms 143 >