< Psalms 142 >
1 Maskili ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú ihò òkúta. Àdúrà. Èmi kígbe sókè sí Olúwa; èmi gbé ohùn mi sókè sí Olúwa fún àánú.
Pieśń pouczająca Dawida, jego modlitwa, gdy był w jaskini. Swoim głosem wołam do PANA; swoim głosem modlę się do PANA.
2 Èmi tú àròyé mí sílẹ̀ níwájú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní èmi fi iṣẹ́ mi hàn níwájú rẹ̀.
Wylewam przed nim swoją troskę i opowiadam mu swoje utrapienie.
3 Nígbà tí ẹ̀mí mi ṣàárẹ̀ nínú mi, ìwọ ni ẹni tí ó mọ ọ̀nà mi. Ní ipa ọ̀nà tí èmi ń rìn ènìyàn ti dẹ okùn fún mi ní ìkọ̀kọ̀.
Gdy mój duch jest we mnie zdruzgotany, ty znasz moją ścieżkę; na drodze, którą chodziłem, zastawili na mnie sidło.
4 Wo ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó sì rì i kò sí ẹni tí ó ṣe àníyàn mi èmi kò ní ààbò; kò sí ẹni tí ó náání ọkàn mi.
Oglądałem się na prawo i spojrzałem, [ale] nie było nikogo, kto mnie znał; nie było dla mnie ucieczki, nikt się nie troszczył o moją duszę.
5 Èmi kígbe sí ọ, Olúwa: èmi wí pé, “Ìwọ ni ààbò mi, ìpín mi ní ilẹ̀ alààyè.”
PANIE, wołam do ciebie, mówiąc: Ty jesteś moją nadzieją, [ty jesteś] moim udziałem w ziemi żyjących.
6 Fi etí sí igbe mi, nítorí tí èmi wà nínú àìnírètí gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi, nítorí wọ́n lágbára jù mí lọ.
Wysłuchaj mego wołania, bo jestem bardzo udręczony; ocal mnie od moich prześladowców, bo są mocniejsi ode mnie.
7 Mú ọkàn mi jáde kúrò nínú túbú, kí èmi lè máa yin orúkọ rẹ. Nígbà náà ni àwọn olódodo yóò yí mi káàkiri nítorí ìwọ yóò fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ba mi ṣe.
Wyprowadź moją duszę z więzienia, abym chwalił twoje imię; sprawiedliwi otoczą mnie, gdy okażesz mi dobroć.