< Psalms 142 >

1 Maskili ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú ihò òkúta. Àdúrà. Èmi kígbe sókè sí Olúwa; èmi gbé ohùn mi sókè sí Olúwa fún àánú.
Hymne de David, lorsqu'il était dans la caverne. — Prière. Ma voix crie vers l'Éternel; Ma voix implore l'Éternel.
2 Èmi tú àròyé mí sílẹ̀ níwájú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní èmi fi iṣẹ́ mi hàn níwájú rẹ̀.
Je répands ma plainte devant lui; J'expose ma détresse en sa présence.
3 Nígbà tí ẹ̀mí mi ṣàárẹ̀ nínú mi, ìwọ ni ẹni tí ó mọ ọ̀nà mi. Ní ipa ọ̀nà tí èmi ń rìn ènìyàn ti dẹ okùn fún mi ní ìkọ̀kọ̀.
Quand je sens mon esprit défaillir en moi. Toi, tu connais le sentier où je marche. Dans le chemin où je m'avance. On m'a tendu un piège.
4 Wo ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó sì rì i kò sí ẹni tí ó ṣe àníyàn mi èmi kò ní ààbò; kò sí ẹni tí ó náání ọkàn mi.
Regarde à ma droite, et vois! Personne ne me reconnaît. Tout refuge me manque; Personne ne prend souci de moi.
5 Èmi kígbe sí ọ, Olúwa: èmi wí pé, “Ìwọ ni ààbò mi, ìpín mi ní ilẹ̀ alààyè.”
Je crie vers toi, ô Éternel, Et je dis: Tu es mon asile. Mon partage sur la terre des vivants.
6 Fi etí sí igbe mi, nítorí tí èmi wà nínú àìnírètí gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ń lépa mi, nítorí wọ́n lágbára jù mí lọ.
Sois attentif à mon cri; Car je suis extrêmement misérable. Délivre-moi de ceux qui me poursuivent; Car ils sont plus forts que moi.
7 Mú ọkàn mi jáde kúrò nínú túbú, kí èmi lè máa yin orúkọ rẹ. Nígbà náà ni àwọn olódodo yóò yí mi káàkiri nítorí ìwọ yóò fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ wọn ba mi ṣe.
Retire mon âme de sa prison, Afin que je puisse célébrer ton nom! Les justes viendront triompher avec moi De ce que tu m'auras comblé de tes bienfaits.

< Psalms 142 >