< Psalms 141 >
1 Saamu ti Dafidi. Olúwa, èmi ké pè ọ́; yára wá sí ọ̀dọ̀ mi. Gbọ́ ohùn mi, nígbà tí mo bá ń ké pè ọ́.
Dāvida dziesma. Kungs, Tevi es piesaucu, steidzies pie manis, klausies uz manu balsi, kad es Tevi piesaucu.
2 Jẹ́ kí àdúrà mi ó wá sí iwájú rẹ bí ẹbọ tùràrí àti ìgbé ọwọ́ mi si òkè rí bí ẹbọ àṣálẹ́.
Lai mana lūgšana Tavā priekšā top cienīta kā kvēpināmais upuris, manu roku pacelšana kā vakara upuris.
3 Fi ẹ̀ṣọ́ ṣọ́ ẹnu mi, Olúwa: kí o sì máa pa ìlẹ̀kùn ètè mi mọ́.
Kungs, sargi manu muti un pasargi manas lūpas.
4 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ohun tí ń ṣe ibi, láti máa bá àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ búburú má sì ṣe jẹ́ kí èmi jẹ àdídùn wọn.
Nedod manai sirdij griezties uz ļaunu, bezdievīgu darbu darīt ar ļaundarītājiem, ka nebaudu no viņu kārumiem.
5 Jẹ́ kí olódodo lù mí, ìṣeun ni ó jẹ́: jẹ́ kí ó bá mi wí, ó jẹ́ òróró ní orí mi. Tí kì yóò fọ́ mi ní orí. Síbẹ̀ àdúrà mi wá láìsí ìṣe àwọn olùṣe búburú.
Lai taisnais mani sit, tā būs žēlastība, un lai viņš mani pārmāca, tā būs eļļa uz manu galvu, tam lai mana galva neliedzās; bet es vienmēr lūdzu pret viņu ļauniem darbiem.
6 A ó ju àwọn alákòóso sílẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ òkúta, àwọn ẹni búburú yóò kọ pé àwọn ọ̀rọ̀ mi dùn.
No akmens kalniem viņu soģi lai top nogāzti; tad dzirdēs manus vārdus, ka tie mīlīgi.
7 Wọn yóò wí pé, “Bí ẹni tí ó la aporo sórí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni egungun wa tànkálẹ̀ ní ẹnu isà òkú.” (Sheol )
Kā zemi uzplēš un uzar, tā mūsu kauli ir izkaisīti līdz pašam kapam. (Sheol )
8 Ṣùgbọ́n ojú mi ń bẹ lára rẹ, Olúwa Olódùmarè; nínú rẹ̀ ni èmi ti rí ààbò, má ṣe fà mi fún ikú.
Bet uz Tevi, Kungs, Dievs, manas acis raugās, uz Tevi paļaujos, neatstum manu dvēseli.
9 Pa mí mọ́ kúrò nínú okùn tí wọn ti dẹ sílẹ̀ fún mi, kúrò nínú ìkẹ́kùn àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
Pasargi mani no tā valga, ko tie man ir izmetuši, un no ļauna darītāju slazdiem.
10 Jẹ́ kí àwọn ẹni búburú ṣubú sínú àwọ̀n ara wọn, nígbà tí èmi bá kọjá lọ láìléwu.
Bezdievīgie kritīs savos tīklos, kamēr es iešu garām.