< Psalms 141 >

1 Saamu ti Dafidi. Olúwa, èmi ké pè ọ́; yára wá sí ọ̀dọ̀ mi. Gbọ́ ohùn mi, nígbà tí mo bá ń ké pè ọ́.
Psaume de David. Éternel, je t'invoque! Accours à mon aide; Prête l'oreille à ma voix, quand je crie vers toi!
2 Jẹ́ kí àdúrà mi ó wá sí iwájú rẹ bí ẹbọ tùràrí àti ìgbé ọwọ́ mi si òkè rí bí ẹbọ àṣálẹ́.
Que ma prière te soit agréable comme l'encens, Et mes mains tendues vers toi, comme l'oblation du soir!
3 Fi ẹ̀ṣọ́ ṣọ́ ẹnu mi, Olúwa: kí o sì máa pa ìlẹ̀kùn ètè mi mọ́.
Éternel, garde ma bouche; Veille sur mes lèvres quand elles s'ouvrent.
4 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ohun tí ń ṣe ibi, láti máa bá àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ búburú má sì ṣe jẹ́ kí èmi jẹ àdídùn wọn.
Ne permets pas que mon coeur soit entraîné au mal, Et qu'il commette des crimes avec les ouvriers d'iniquité. Que je ne prenne aucune part à leurs festins!
5 Jẹ́ kí olódodo lù mí, ìṣeun ni ó jẹ́: jẹ́ kí ó bá mi wí, ó jẹ́ òróró ní orí mi. Tí kì yóò fọ́ mi ní orí. Síbẹ̀ àdúrà mi wá láìsí ìṣe àwọn olùṣe búburú.
Que le juste me frappe, ce sera une faveur pour moi; Qu'il me reprenne, ce sera de l'huile sur ma tête; Ma tête ne se détournera pas! Car, même en face des persécutions des méchants. Je ne fais que prier.
6 A ó ju àwọn alákòóso sílẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ òkúta, àwọn ẹni búburú yóò kọ pé àwọn ọ̀rọ̀ mi dùn.
Leurs chefs seront précipités sur les flancs des rochers! Alors on écoutera mes paroles; Car elles sont pleines de douceur.
7 Wọn yóò wí pé, “Bí ẹni tí ó la aporo sórí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni egungun wa tànkálẹ̀ ní ẹnu isà òkú.” (Sheol h7585)
Comme la terre labourée et fendue par la charrue, Nos os sont dispersés à l'entrée du Sépulcre. (Sheol h7585)
8 Ṣùgbọ́n ojú mi ń bẹ lára rẹ, Olúwa Olódùmarè; nínú rẹ̀ ni èmi ti rí ààbò, má ṣe fà mi fún ikú.
C'est vers toi, Éternel, ô Seigneur, Que se tournent mes regards. Je cherche un refuge auprès de toi: N'abandonne pas mon âme!
9 Pa mí mọ́ kúrò nínú okùn tí wọn ti dẹ sílẹ̀ fún mi, kúrò nínú ìkẹ́kùn àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
Garde-moi du piège qu'ils m'ont tendu, Et des embûches des ouvriers d'iniquité!
10 Jẹ́ kí àwọn ẹni búburú ṣubú sínú àwọ̀n ara wọn, nígbà tí èmi bá kọjá lọ láìléwu.
Puissent les méchants tomber dans leurs propres filets, Pendant que moi, je parviendrai à m'enfuir!

< Psalms 141 >