< Psalms 141 >
1 Saamu ti Dafidi. Olúwa, èmi ké pè ọ́; yára wá sí ọ̀dọ̀ mi. Gbọ́ ohùn mi, nígbà tí mo bá ń ké pè ọ́.
Psaume de David. Seigneur, j'ai crié vers toi, écoute-moi; sois attentif à la voix de ma prière, quand je crie vers toi.
2 Jẹ́ kí àdúrà mi ó wá sí iwájú rẹ bí ẹbọ tùràrí àti ìgbé ọwọ́ mi si òkè rí bí ẹbọ àṣálẹ́.
Que ma prière se dirige vers toi, comme de l'encens; que l'élévation de mes mains vers toi soit comme le sacrifice du soir.
3 Fi ẹ̀ṣọ́ ṣọ́ ẹnu mi, Olúwa: kí o sì máa pa ìlẹ̀kùn ètè mi mọ́.
Mets, Seigneur, une garde à ma bouche, et une porte de sûreté autour de mes lèvres.
4 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ohun tí ń ṣe ibi, láti máa bá àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ búburú má sì ṣe jẹ́ kí èmi jẹ àdídùn wọn.
N'incline pas mon cœur vers les paroles de la malice, pour trouver des prétextes à mes péchés, en compagnie des ouvriers d'iniquité; préserve-moi d'entrer en communication avec ceux de leur choix.
5 Jẹ́ kí olódodo lù mí, ìṣeun ni ó jẹ́: jẹ́ kí ó bá mi wí, ó jẹ́ òróró ní orí mi. Tí kì yóò fọ́ mi ní orí. Síbẹ̀ àdúrà mi wá láìsí ìṣe àwọn olùṣe búburú.
Que le juste me réprimande avec miséricorde, et me blâme de même; mais que l'huile des pécheurs ne parfume point ma tête, que ma prière soit toujours en opposition avec leurs cupidités.
6 A ó ju àwọn alákòóso sílẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ òkúta, àwọn ẹni búburú yóò kọ pé àwọn ọ̀rọ̀ mi dùn.
Leurs puissants ont été précipités près des rochers; ils écouteront mes paroles, parce qu'elles sont adoucies.
7 Wọn yóò wí pé, “Bí ẹni tí ó la aporo sórí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni egungun wa tànkálẹ̀ ní ẹnu isà òkú.” (Sheol )
Comme les glèbes de la terre sont brisées sur la terre, nos os ont été dispersés aux portes de l'enfer. (Sheol )
8 Ṣùgbọ́n ojú mi ń bẹ lára rẹ, Olúwa Olódùmarè; nínú rẹ̀ ni èmi ti rí ààbò, má ṣe fà mi fún ikú.
Seigneur, Seigneur, mes yeux sont tournés vers toi; j'ai espéré en toi; ne prends point ma vie.
9 Pa mí mọ́ kúrò nínú okùn tí wọn ti dẹ sílẹ̀ fún mi, kúrò nínú ìkẹ́kùn àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
Garde-moi des fils qu'on a tendus contre moi, et de la pierre de scandale des ouvriers d'iniquité.
10 Jẹ́ kí àwọn ẹni búburú ṣubú sínú àwọ̀n ara wọn, nígbà tí èmi bá kọjá lọ láìléwu.
Que les pécheurs tombent dans leurs propres filets; pour moi, je vais seul jusqu'à ce que je passe.