< Psalms 141 >

1 Saamu ti Dafidi. Olúwa, èmi ké pè ọ́; yára wá sí ọ̀dọ̀ mi. Gbọ́ ohùn mi, nígbà tí mo bá ń ké pè ọ́.
Un psaume de David. Yahvé, je t'ai invoqué. Viens vite me voir! Écoute ma voix quand je t'appelle.
2 Jẹ́ kí àdúrà mi ó wá sí iwájú rẹ bí ẹbọ tùràrí àti ìgbé ọwọ́ mi si òkè rí bí ẹbọ àṣálẹ́.
Que ma prière soit présentée devant toi comme un encens; l'élévation de mes mains comme le sacrifice du soir.
3 Fi ẹ̀ṣọ́ ṣọ́ ẹnu mi, Olúwa: kí o sì máa pa ìlẹ̀kùn ètè mi mọ́.
Veille, Yahvé, sur ma bouche. Garde la porte de mes lèvres.
4 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ohun tí ń ṣe ibi, láti máa bá àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ búburú má sì ṣe jẹ́ kí èmi jẹ àdídùn wọn.
N'incline pas mon cœur à quelque chose de mauvais, pour pratiquer des actes de méchanceté avec des hommes qui font l'iniquité. Ne me laissez pas manger de leurs délices.
5 Jẹ́ kí olódodo lù mí, ìṣeun ni ó jẹ́: jẹ́ kí ó bá mi wí, ó jẹ́ òróró ní orí mi. Tí kì yóò fọ́ mi ní orí. Síbẹ̀ àdúrà mi wá láìsí ìṣe àwọn olùṣe búburú.
Que le juste me frappe, c'est de la bonté; qu'il me réprimande, c'est comme de l'huile sur la tête; ne laisse pas ma tête la refuser; Pourtant, ma prière est toujours contre les mauvaises actions.
6 A ó ju àwọn alákòóso sílẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ òkúta, àwọn ẹni búburú yóò kọ pé àwọn ọ̀rọ̀ mi dùn.
Leurs juges sont jetés sur les flancs du rocher. Ils entendront mes paroles, car elles sont bien prononcées.
7 Wọn yóò wí pé, “Bí ẹni tí ó la aporo sórí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni egungun wa tànkálẹ̀ ní ẹnu isà òkú.” (Sheol h7585)
« Comme lorsqu'on laboure et qu'on brise la terre, nos os sont dispersés à l'entrée du séjour des morts. » (Sheol h7585)
8 Ṣùgbọ́n ojú mi ń bẹ lára rẹ, Olúwa Olódùmarè; nínú rẹ̀ ni èmi ti rí ààbò, má ṣe fà mi fún ikú.
Car mes yeux sont fixés sur toi, Yahvé, le Seigneur. Je me réfugie en toi. Ne laisse pas mon âme démunie.
9 Pa mí mọ́ kúrò nínú okùn tí wọn ti dẹ sílẹ̀ fún mi, kúrò nínú ìkẹ́kùn àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
Garde-moi du piège qu'ils m'ont tendu, des pièges des ouvriers de l'iniquité.
10 Jẹ́ kí àwọn ẹni búburú ṣubú sínú àwọ̀n ara wọn, nígbà tí èmi bá kọjá lọ láìléwu.
Queles méchants tombent ensemble dans leurs propres filets. pendant que je passe.

< Psalms 141 >