< Psalms 140 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
Para o músico chefe. Um Salmo de David. Deliver me, Yahweh, de homens maus. Preservar-me de homens violentos:
2 ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
aqueles que inventam travessuras em seus corações. Eles se reúnem continuamente para a guerra.
3 Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
Eles afiaram suas línguas como uma serpente. O veneno da víbora está sob seus lábios. (Selah)
4 Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
Yahweh, me afaste das mãos dos ímpios. Preserve-me dos homens violentos que determinaram tropeçar em meus pés.
5 Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
Os orgulhosos esconderam uma armadilha para mim, eles espalharam as cordas de uma rede pelo caminho. Eles montaram armadilhas para mim. (Selah)
6 Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
Eu disse a Javé: “Você é meu Deus”. Ouça o grito das minhas petições, Yahweh.
7 Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
Yahweh, o Senhor, a força da minha salvação, você cobriu minha cabeça no dia da batalha.
8 Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
Yahweh, não conceda os desejos dos ímpios. Não deixe que seus planos maléficos tenham sucesso, ou eles se tornarão orgulhosos. (Selah)
9 Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Quanto à cabeça daqueles que me cercam, deixar que a maldade de seus próprios lábios os cubra.
10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
Let carvões queimados caem sobre eles. Que sejam atirados ao fogo, em fossos de lata, de onde eles nunca se levantam.
11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
Um orador maligno não será estabelecido na terra. O mal vai caçar o homem violento para derrubá-lo.
12 Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
Eu sei que Yahweh manterá a causa dos aflitos, e justiça para os necessitados.
13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.
Certamente, os justos agradecerão seu nome. Os verticalizados habitarão em sua presença.

< Psalms 140 >