< Psalms 140 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
Thaburi ya Daudi Wee Jehova, hatũra kuuma moko-inĩ ma andũ arĩa ooru; ngitĩra harĩ andũ arĩa mahũthagĩra ũhinya,
2 ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
o acio mathugundaga maũndũ mooru ngoro-inĩ ciao, na magathugunda mbaara o mũthenya.
3 Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
Manooraga nĩmĩ ciao ikohĩga ta rũrĩmĩ rwa nyoka; mĩromo yao yaragia maũndũ marũrũ ta thumu wa nduĩra.
4 Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
Wee Jehova, njeheria moko-inĩ ma andũ arĩa aaganu; ngitĩra kuuma harĩ andũ arĩa mahũthagĩra ũhinya, o acio mabangaga ũrĩa mangĩhĩnga magũrũ makwa.
5 Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
Andũ arĩa etĩĩi nĩmanyambĩire mũtego; nĩmatambũrũkĩtie ndigi cia wabu wao, na makanjigĩra mĩtego njĩra-inĩ yakwa.
6 Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
Wee Jehova, nguuga atĩrĩ, “Wee nĩwe Mũrungu wakwa.” Wee Jehova-rĩ, igua ngĩgũkaĩra nĩguo, ũnjiguĩre tha.
7 Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
Wee Mwathani Jehova, o Wee ũrĩa mũũhonokia ũrĩ hinya, Wee ũgitagĩra mũtwe wakwa mũthenya wa mbaara:
8 Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
Wee Jehova, ndũkahingĩrie arĩa aaganu merirĩria mao, ndũkareke mĩbango yao ĩgaacĩre, matikae gwĩtĩĩa.
9 Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Mĩtwe ya arĩa mandigicĩirie ĩrohumbĩkanio na mathĩĩna marĩa marehetwo nĩ mĩromo yao.
10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
Marogwĩrwo nĩ makara me gwakana; maroikio mwaki-inĩ, maikio marima marĩ mũtondo, kũrĩa matakoima o na rĩ.
11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
Ndũkanareke arĩa macambanagia magaacĩre bũrũri-inĩ; mwanangĩko ũrothingata andũ arĩa mahũthagĩra ũhinya.
12 Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
Niĩ nĩnjũũĩ atĩ Jehova nĩarũagĩra kĩhooto kĩa arĩa athĩĩni, na akagitĩra kĩhooto kĩa arĩa abatari.
13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.
Ti-itherũ arĩa athingu nĩmarĩgoocaga rĩĩtwa rĩaku, na arĩa arũngĩrĩru nĩmagatũũra ũthiũ-inĩ waku.

< Psalms 140 >