< Psalms 140 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
Au maître-chantre. — Psaume de David. Éternel, délivre-moi de l'homme méchant. Et préserve-moi de l'homme violent,
2 ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
De ceux qui méditent le mal dans leur coeur. Et qui suscitent tous les jours des querelles;
3 Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
De ceux qui ont la langue affilée comme celle du serpent. Qui ont un venin d'aspic sous leurs lèvres. (Pause)
4 Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
Éternel, sauve-moi des mains du méchant; Préserve-moi de l'homme violent. De ceux qui ne pensent qu'à me faire tomber.
5 Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
Les orgueilleux ont dressé contre moi des pièges et des lacets; Ils ont tendu des filets sur le bord du chemin; Ils ont posé contre moi des embûches. (Pause)
6 Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
J'ai dit à l'Éternel: Tu es mon Dieu! Prête l'oreille, ô Éternel, à ma voix suppliante!
7 Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
Seigneur, Éternel, mon puissant libérateur, Tu protèges ma tête au jour de la bataille.
8 Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
Éternel, n'exauce pas les souhaits du méchant; Ne laisse pas réussir ses desseins, De peur qu'il n'en tire vanité! (Pause)
9 Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Fais tomber sur la tête de ceux qui m'assiègent Les maux dont leurs lèvres m'ont menacé!
10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
Qu'on jette sur eux des charbons embrasés! Qu'on les précipite dans le feu, Dans les flots profonds d'où ils ne pourront plus s'échapper.
11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
Le calomniateur ne fera que passer sur la terre; Le malheur poursuivra sans relâche l'homme violent;
12 Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
Mais je sais que l'Éternel fera droit au misérable. Qu'il fera justice au malheureux.
13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.
Oui, les justes célébreront ton nom; Les hommes droits seront en sécurité. En ta présence.

< Psalms 140 >