< Psalms 140 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
Yahweh, rescue/save me from [being attacked by] evil men; and [even more], (keep me safe/protect me) from being attacked by violent people.
2 ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
They are always planning to do evil things and they are always inciting/urging people to start quarrels.
3 Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
By what they say [MTY] [they injure people like] poisonous snakes do; the words that they speak [MTY] [can kill people as easily as] cobras/vipers do.
4 Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
Yahweh, protect me from the power [MTY] of wicked [people]. Keep me safe from violent men who plan to destroy me [SYN].
5 Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
[It is as though] proud people have set a trap for me; [it is as though] they have spread their nets to catch me; [it is as though] they have put those things along the road to catch/seize me.
6 Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
I say to you, “Yahweh, you are my God;” [so] listen to me while I cry out to you to help me.
7 Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
Yahweh, my Lord, you are the one who defends me strongly; you have [protected me] during battles [MET] [as though you had put a helmet on] my head.
8 Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
Yahweh, do allow wicked [people] to do the things that they desire, and do not allow them to do the [evil things that] they plan to do.
9 Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
[Do not allow] my enemies to (become proud/defeat me); cause the evil things that they say [MTY] they will do to me to happen to them, [instead].
10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
Cause burning coals to fall on their [heads]! Cause them to be thrown into deep pits, from which they cannot climb out!
11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
Do not allow those who slander others to succeed; cause evil things to happen to violent men and destroy them!
12 Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
Yahweh, I know that you defend those who are oppressed, and that you do what is just/fair for those who are needy/poor.
13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.
Righteous [people] will surely thank you [MTY], and they will live (in your presence/with you).

< Psalms 140 >