< Psalms 140 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
Aw Bawipa, thlakchekhqi kut khuiawh kawng ni hul lah; boeksekhqi a kut khui awhkawng nang ing nik chung lah,
2 ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
ak kawlung khuiawh ak che poeknaak doeng ta unawh myngawi qaal na tho loet uhy.
3 Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
A mim laikhqi ce khqui am lai amyihna hqat sak unawh; khquihse a chy ce ami hui kqang awm hy.
4 Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
Aw Bawipa, thlakchekhqi kut khui awhkawng nang ing ni khoem lah; kai a khawkham lawlh sak aham ak cai thlakchekhqi anglakawhkawng ni hlip lah.
5 Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
Ak oek qukhqi ing kai aham ang hyp na dawng dun law unawh; lawk qui ce zan law uhy, ka cehnaak lam boeih awh dun law uhy.
6 Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
Aw Bawipa, nang a venawh, “Nang taw ka Khawsa ni,” ti nyng. Aw Bawipa, qeennaak thoeh doena kang kqangnaak awi ve ngai law lah.
7 Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
Aw Boeimang Khawsa, kai anik hulkung thakawm, qal tuknaak kung awh ka lu ak dah lawkung –
8 Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
Aw Bawipa, thlakchekhqi a ngaihnaak ce koeh soep law pe sak; a ming cainaak awm koeh coeng sak, cemyih am mantaw oek qu hau kawm uh.
9 Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
Kai anik chungkhqi a lukhqi taw a mimah a hui ing ang coeng sak kyinaak ing sing pe seh.
10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
Maikqawng ce a mingmih ak khan awh tlaak pe seitaw; a mami thawh thai voel aham mai awh, lawk-kqawng khuina khawng u seh.
11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
Qam khuiawh thlang kqawnseet na ak nget khqi ce koeh awm seh; boeksekhqi taw seetnaak ing a hu awh hquut seh.
12 Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
Bawipa ing thymnaak ce khawdengkhqi ham taak pe nawh ak voethlauhkhqi ce dawm a hlai hy tice sim nyng.
13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.
Thlakdyngkhqi ing nang ang ming ce kyihcah kawm usaw thlak leek khqi ce na haiawh awm kawm uh.

< Psalms 140 >