< Psalms 14 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Aṣiwèrè wí nínú ọkàn rẹ̀ pé, “Ko sí Ọlọ́run.” Wọ́n díbàjẹ́, iṣẹ́ wọn sì burú; kò sí ẹnìkan tí yóò ṣe rere.
Kumqondisi wokuhlabela. KaDavida. Isiwula sithi enhliziyweni yaso, “AkulaNkulunkulu.” Baxhwalile, izenzo zabo zibolile; kakho loyedwa owenza okuhle.
2 Olúwa sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run wá lórí àwọn ọmọ ènìyàn bóyá ó le rí ẹni tí òye yé, ẹnikẹ́ni tó ń wá Ọlọ́run.
UThixo ukhangela phansi esezulwini emadodaneni abantu ingabe bakhona yini abazwisisayo, abamdingayo uNkulunkulu.
3 Gbogbo wọn sì ti yípadà, gbogbo wọn sì ti díbàjẹ́; kò sì ṣí ẹni tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.
Bonke baphambukile, bonke sebexhwalile; kakho loyedwa owenza okuhle, kakho lamunye.
4 Ǹjẹ́ olùṣe búburú kò ha ní ìmọ̀? Àwọn tí ó ń pa ènìyàn mi jẹ bí ẹní jẹun; wọn kò sì ké pe Olúwa?
Kanti lezizixhwali kaziyikufa zafunda yini? Zona ezidla abantu bami ingathi zidla isinkwa, ezingamkhonziyo uThixo.
5 Wọ́n wà níbẹ̀, tí a bò mọ́lẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù, nítorí Ọlọ́run wà ní àwùjọ àwọn olódodo.
Kodwa yibo abagubhazeliswa luvalo ngoba uNkulunkulu ukhona phakathi kwabalungileyo.
6 Ẹ̀yin olùṣe búburú da èrò àwọn tálákà rú, ṣùgbọ́n Olúwa ni ààbò wọn.
Lina benzi bobubi lifubisa amalungiselelo abayanga, kodwa uThixo uyisiphephelo sabo.
7 Ìgbàlà àwọn Israẹli yóò ti Sioni wá! Nígbà tí Olúwa bá mú ìkólọ àwọn ènìyàn rẹ̀ padà, jẹ́ kí Jakọbu kí ó yọ̀, kí inú Israẹli kí ó dùn!
Awu, sengathi insindiso ka-Israyeli ingaqhamuka eZiyoni! Nxa uThixo esebuyisela impumelelo yabantu bakhe, kathokoze uJakhobe lo-Israyeli ajabule!

< Psalms 14 >