< Psalms 14 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Aṣiwèrè wí nínú ọkàn rẹ̀ pé, “Ko sí Ọlọ́run.” Wọ́n díbàjẹ́, iṣẹ́ wọn sì burú; kò sí ẹnìkan tí yóò ṣe rere.
Přednímu zpěváku, píseň Davidova. Říká blázen v srdci svém: Není Boha. Porušeni jsou, a ohavní v snažnostech; není, kdo by činil dobré.
2 Olúwa sì bojú wolẹ̀ láti ọ̀run wá lórí àwọn ọmọ ènìyàn bóyá ó le rí ẹni tí òye yé, ẹnikẹ́ni tó ń wá Ọlọ́run.
Hospodin s nebe popatřil na syny lidské, aby viděl, byl-li by kdo rozumný a hledající Boha.
3 Gbogbo wọn sì ti yípadà, gbogbo wọn sì ti díbàjẹ́; kò sì ṣí ẹni tí ó ń ṣe rere, kò sí ẹnìkan.
Všickni se odvrátili, napořád neužiteční učiněni jsou; není, kdo by činil dobré, není ani jednoho.
4 Ǹjẹ́ olùṣe búburú kò ha ní ìmọ̀? Àwọn tí ó ń pa ènìyàn mi jẹ bí ẹní jẹun; wọn kò sì ké pe Olúwa?
Zdaliž nevědí všickni činitelé nepravosti, že zžírají lid můj, jako by chléb jedli? Hospodina pak nevzývají.
5 Wọ́n wà níbẹ̀, tí a bò mọ́lẹ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù, nítorí Ọlọ́run wà ní àwùjọ àwọn olódodo.
Tehdáž se náramně strašiti budou; nebo Bůh jest v rodině spravedlivého.
6 Ẹ̀yin olùṣe búburú da èrò àwọn tálákà rú, ṣùgbọ́n Olúwa ni ààbò wọn.
Radu chudého potupujete, ale Hospodin jest naděje jeho.
7 Ìgbàlà àwọn Israẹli yóò ti Sioni wá! Nígbà tí Olúwa bá mú ìkólọ àwọn ènìyàn rẹ̀ padà, jẹ́ kí Jakọbu kí ó yọ̀, kí inú Israẹli kí ó dùn!
Ó by z Siona dáno bylo spasení Izraelovi. Když Hospodin zase přivede zajaté lidu svého, plésati bude Jákob, a veseliti se Izrael.

< Psalms 14 >