< Psalms 139 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Olúwa, ìwọ tí wádìí mi, ìwọ sì ti mọ̀ mí.
Drottinn, þú rannsakar mig út og inn og veist allt um mig.
2 Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi, ìwọ mọ̀ èrò mi ní ọ̀nà jíjìn réré.
Hvort ég sit eða stend, það veist þú. Og þú lest hugsanir mínar úr fjarlægð!
3 Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi, gbogbo ọ̀nà mi sì di mí mọ̀ fún ọ.
Þú veist hvert ég stefni og þekkir langanir mínar. Og hvort sem ég geng eða ligg, þá athugar þú það. Þú veist öllum stundum hvar ég er.
4 Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi, kíyèsi i, Olúwa, ìwọ mọ̀ ọ́n pátápátá.
Þú þekkir orðin á tungu minni áður en ég opna munninn!
5 Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú, ìwọ sì fi ọwọ́ rẹ lé mi.
Þú bæði fylgir mér og ferð á undan mér, leggur hönd þína á höfuð mitt og blessar mig.
6 Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù; ó ga, èmi kò le mọ̀ ọ́n.
Þetta er stórkostlegt! Já, næstum of gott til að vera satt!
7 Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ? Tàbí níbo ni èmi yóò sáré kúrò níwájú rẹ?
Hvert get ég farið frá anda þínum eða flúið frá augliti þínu?
8 Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀; bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú, kíyèsi i, ìwọ wà níbẹ̀ pẹ̀lú. (Sheol h7585)
Fari ég til himna, þá ertu þar, til dánarheima, þá ertu líka þar! (Sheol h7585)
9 Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀, kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin Òkun,
Ef ég svifi á skýjum morgunroðans og settist við fjarlæga strönd,
10 àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì dì mímú.
einnig þar mundi hönd þín leiða mig og ég finna styrk þinn og vernd.
11 Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀; kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.”
Og þótt ég reyndi að læðast frá þér inn í myrkrið, þá myndi nóttin lýsa eins og dagur!
12 Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ; ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán; àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjì bákan náà ní fún ọ.
Því að myrkrið hylur ekkert fyrir Guði, dagur og nótt eru jöfn fyrir þér.
13 Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi; ìwọ ni ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.
Öll líffæri mín hefur þú skapað, ofið þau í kviði móður minnar.
14 Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi; ìyanu ní iṣẹ́ rẹ; èyí nì ni ọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú.
Þökk, að þú skapaðir mig eins undursamlega og raun ber vitni! Þetta er dásamlegt um að hugsa! Handaverk þín eru stórkostleg – það er mér alveg ljóst.
15 Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ, nígbà tí a dá mi ní ìkọ̀kọ̀. Tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà ní ìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
Þú varst til staðar þegar ég var myndaður í leyni.
16 ojú rẹ ti rí ohun ara mi nígbà tí a kò tí ì ṣe mí pé, àti nínú ìwé rẹ ni a ti kọ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí, ní ọjọ́ tí a dá wọn, nígbà tí wọn kò tilẹ̀ tí ì sí.
Þú þekktir mig þegar ég var fóstur í móðurkviði og áður en ég sá dagsins ljós hafðir þú ákvarðað alla mína ævidaga – sérhver dagur var skráður í bók þína!
17 Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi, iye wọn ti pọ̀ tó!
Hugsanir þínar, ó Guð, eru mér torskildar, en samt eru þær stórkostlegar!
18 Èmi ìbá kà wọ́n, wọ́n ju iyanrìn lọ ní iye: nígbà tí mo bá jí, èmi yóò wà lọ́dọ̀ rẹ síbẹ̀.
Ef ég reyndi að telja þær, þá yrði það mér ofviða því að þær eru fleiri en sandkorn á sjávarströnd! Já, ég mundi vakna eins og af draumi, en hugur minn, hann væri enn hjá þér!
19 Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́; nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹlẹ́jẹ̀.
Vissulega munt þú, Guð, útrýma níðingunum. Já, burt með ykkur, þið morðingjar!
20 Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ, àwọn ọ̀tá rẹ ń pe orúkọ rẹ ní asán!
Þeir guðlasta og hreykja sér upp gegn þér – hvílík heimska!
21 Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ? Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?
Drottinn, ætti ég ekki að hata þá sem þig hata? Og ætti ég ekki að hafa viðbjóð á þeim?
22 Èmi kórìíra wọn ní àkótán; èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.
Jú, ég hata þá, því að þínir óvinir eru mínir óvinir.
23 Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí; dán mi wò, kí o sì mọ ìrò inú mi.
Prófaðu mig Guð. Rannsakaðu hjarta mitt og hugsanir mínar.
24 Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú kan bá wà nínú mi kí ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.
Sýndu mér það í fari mínu sem hryggir þig og leiddu mig svo áfram veginn til eilífs lífs.

< Psalms 139 >