< Psalms 139 >
1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Olúwa, ìwọ tí wádìí mi, ìwọ sì ti mọ̀ mí.
Au maître-chantre. — Psaume de David. Éternel, tu m'as sondé, et tu m'as connu.
2 Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi, ìwọ mọ̀ èrò mi ní ọ̀nà jíjìn réré.
Tu sais quand je m'assieds et quand je me lève; Tu découvres de loin ma pensée.
3 Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi, gbogbo ọ̀nà mi sì di mí mọ̀ fún ọ.
Tu m'observes, soit que je marche, soit que je me couche; Tu as une parfaite connaissance de toutes mes actions.
4 Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi, kíyèsi i, Olúwa, ìwọ mọ̀ ọ́n pátápátá.
Même avant que la parole soit sur ma langue, Déjà, ô Éternel, tu la connais tout entière.
5 Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú, ìwọ sì fi ọwọ́ rẹ lé mi.
Tu es à mes côtés, et par derrière et par devant; Tu poses ta main sur moi.
6 Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù; ó ga, èmi kò le mọ̀ ọ́n.
Une telle science est trop merveilleuse pour moi. Trop élevée pour que je puisse y atteindre!
7 Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ? Tàbí níbo ni èmi yóò sáré kúrò níwájú rẹ?
Où irais-je loin de ton Esprit, Où fuirais-je loin de ta face?
8 Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀; bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú, kíyèsi i, ìwọ wà níbẹ̀ pẹ̀lú. (Sheol )
Si je monte aux cieux, tu y es; Si je me couche dans le Sépulcre, t'y voilà! (Sheol )
9 Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀, kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin Òkun,
Si je prenais les ailes de l'aurore. Et si j'allais demeurer à l'extrémité de la mer,
10 àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì dì mímú.
Là même, ta main me conduirait. Ta main droite me saisirait!
11 Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀; kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.”
Si je dis: «Seules les ténèbres pourront me cacher.» — Alors, la nuit même devient lumière autour de moi.
12 Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ; ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán; àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjì bákan náà ní fún ọ.
Pour toi les ténèbres ne sont pas obscures: La nuit resplendit comme le jour, Et les ténèbres comme la lumière!
13 Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi; ìwọ ni ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.
Car c'est toi qui as formé mes reins, Qui m'as tissé dans le sein de ma mère.
14 Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi; ìyanu ní iṣẹ́ rẹ; èyí nì ni ọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú.
Je te loue de ce que tu as fait de mon corps Une oeuvre si étonnante et si merveilleuse. Oui, tes oeuvres sont merveilleuses, Et mon âme ne se lasse pas de le reconnaître.
15 Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ, nígbà tí a dá mi ní ìkọ̀kọ̀. Tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà ní ìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
La structure de mon corps n'était pas ignorée de toi, Lorsque j'étais formé dans le secret, Et tissé comme dans des entrailles souterraines,
16 ojú rẹ ti rí ohun ara mi nígbà tí a kò tí ì ṣe mí pé, àti nínú ìwé rẹ ni a ti kọ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí, ní ọjọ́ tí a dá wọn, nígbà tí wọn kò tilẹ̀ tí ì sí.
Tes yeux m'ont vu, lorsque je n'étais qu'un peloton. Et sur ton livre étaient inscrits Tous les jours qui m'étaient réservés, Avant qu'un seul de ces jours existât.
17 Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi, iye wọn ti pọ̀ tó!
Que tes pensées me sont précieuses, ô Dieu, Et combien leur nombre est immense!
18 Èmi ìbá kà wọ́n, wọ́n ju iyanrìn lọ ní iye: nígbà tí mo bá jí, èmi yóò wà lọ́dọ̀ rẹ síbẹ̀.
Pourrais-je les compter? Elles sont plus nombreuses que les grains de sable! Quand je me réveille, elles occupent encore mon esprit.
19 Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́; nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹlẹ́jẹ̀.
Dieu, ne feras-tu pas mourir le méchant? Hommes de sang, éloignez-vous de moi!
20 Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ, àwọn ọ̀tá rẹ ń pe orúkọ rẹ ní asán!
Ils se servent de ton nom pour mal faire; Tes ennemis l'invoquent pour mentir.
21 Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ? Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?
Éternel, comment ne haïrais-je pas ceux qui te haïssent, Et n'aurais-je pas en horreur ceux qui s'élèvent contre toi?
22 Èmi kórìíra wọn ní àkótán; èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.
Je les hais d'une parfaite haine; Je les tiens pour mes ennemis.
23 Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí; dán mi wò, kí o sì mọ ìrò inú mi.
Sonde-moi, ô Dieu fort, et connais mon coeur; Éprouve-moi, et connais mes pensées.
24 Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú kan bá wà nínú mi kí ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.
Regarde si je suis sur une voie funeste. Et conduis-moi dans la voie de l'éternité!