< Psalms 139 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Olúwa, ìwọ tí wádìí mi, ìwọ sì ti mọ̀ mí.
За първия певец. Давидов псалом. Господи, опитал си ме и познал си ме.
2 Ìwọ mọ̀ ìjókòó mi àti ìdìde mi, ìwọ mọ̀ èrò mi ní ọ̀nà jíjìn réré.
Ти познаваш сядянето ми и ставането ми; Разбираш помислите ми от далеч,
3 Ìwọ yí ipa ọ̀nà mi ká àti ìdùbúlẹ̀ mi, gbogbo ọ̀nà mi sì di mí mọ̀ fún ọ.
Издирваш ходенето ми и лягането ми, И знаеш всичките ми пътища.
4 Nítorí tí kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ahọ́n mi, kíyèsi i, Olúwa, ìwọ mọ̀ ọ́n pátápátá.
Защото докато думата не е още на езика ми, Ето, Господи, Ти я знаеш цяла.
5 Ìwọ sé mi mọ́ lẹ́yìn àti níwájú, ìwọ sì fi ọwọ́ rẹ lé mi.
Ти си пред мен и зад мен, И турил си върху мене ръката Си.
6 Irú ìmọ̀ yìí jẹ ohun ìyanu fún mi jù; ó ga, èmi kò le mọ̀ ọ́n.
Това знание е прочуто за мене; Високо е; не мога да го стигна.
7 Níbo ní èmi yóò gbé lọ kúrò ni ọwọ́ ẹ̀mí rẹ? Tàbí níbo ni èmi yóò sáré kúrò níwájú rẹ?
Къде да отида от твоя Дух? Или от присъствието Ти къде да побягна?
8 Bí èmi bá gòkè lọ sí ọ̀run, ìwọ wà níbẹ̀; bí èmí ba sì tẹ́ ẹní mi ní ipò òkú, kíyèsi i, ìwọ wà níbẹ̀ pẹ̀lú. (Sheol h7585)
Ако възляза на небето, Ти си там; Ако си постеля в преизподнята и там си Ти. (Sheol h7585)
9 Èmi ìbá mú ìyẹ́ apá òwúrọ̀, kí èmi sì lọ jókòó ní ìhà òpin Òkun,
Ако взема крилата на зората И се заселя в най-далечните краища на морето,
10 àní, níbẹ̀ náà ni ọwọ́ rẹ̀ yóò fà mí ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì dì mímú.
Там ще ме води ръката Ти, И Твоята десница не ме държи.
11 Bí mo bá wí pé, “Ǹjẹ́ kí òkùnkùn kí ó bò mí mọ́lẹ̀; kí ìmọ́lẹ̀ kí ó di òru yí mi ká.”
Ако река: Поне тъмнината ще ме покрие, И светлината около мене ще стане на нощ,
12 Nítòótọ́ òkùnkùn kì í ṣú lọ́dọ̀ rẹ; ṣùgbọ́n òru tan ìmọ́lẹ̀ bí ọ̀sán; àti òkùnkùn àti ọ̀sán, méjèèjì bákan náà ní fún ọ.
То и самата тъмнина не укрива нищо от Тебе, А нощта свети като деня; За Тебе тъмнината и светлината са безразлични.
13 Nítorí ìwọ ni ó dá ọkàn mi; ìwọ ni ó bò mí mọ́lẹ̀ nínú ìyá mi.
Защото Ти си образувал чреслата ми, Обвил си ме в утробата на майка ми.
14 Èmi yóò yìn ọ, nítorí tẹ̀rù tẹ̀rù àti tìyanu tìyanu ní a dá mi; ìyanu ní iṣẹ́ rẹ; èyí nì ni ọkàn mi sì mọ̀ dájúdájú.
Ще Те славя, защото страшно и чудно съм направен; Чудни са Твоите дела, И душата ми добре знае това.
15 Ẹ̀dá ara mi kò pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ rẹ, nígbà tí a dá mi ní ìkọ̀kọ̀. Tí a sì ń ṣiṣẹ́ ní àràbarà ní ìhà ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé,
Костникът ми не се укри от Тебе, Когато в тайна се работех, И в дълбочина на земята ми се даваше разнообразната ми форма.
16 ojú rẹ ti rí ohun ara mi nígbà tí a kò tí ì ṣe mí pé, àti nínú ìwé rẹ ni a ti kọ ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sí, ní ọjọ́ tí a dá wọn, nígbà tí wọn kò tilẹ̀ tí ì sí.
Твоите очи видяха необразуваното ми вещество; И в твоята книга бяха записани Всичките ми определени дни, Докато още не съществуваше ни един от тях.
17 Ọlọ́run, èrò inú rẹ tí ṣe iyebíye tó fún mi, iye wọn ti pọ̀ tó!
И колко скъпоценни за мене са тия Твои помисли, Боже! Колко голямо е числото им!
18 Èmi ìbá kà wọ́n, wọ́n ju iyanrìn lọ ní iye: nígbà tí mo bá jí, èmi yóò wà lọ́dọ̀ rẹ síbẹ̀.
Ако бях поискал да ги изброя, те са по-многобройни от пясъка; Събуждам ли, се още съм с Тебе.
19 Ọlọ́run ìbá jẹ́ pa àwọn ènìyàn búburú nítòótọ́; nítorí náà kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin ọkùnrin ẹlẹ́jẹ̀.
Непременно ще поразиш нечестивите Боже; Отдалечете се, прочее, от мене, мъже кръвопийци.
20 Ẹni tí ń fi inú búburú sọ̀rọ̀ sí ọ, àwọn ọ̀tá rẹ ń pe orúkọ rẹ ní asán!
Защото говорят против Тебе нечестиво, И враговете Ти се подигат против Тебе заради суета.
21 Olúwa, ǹjẹ́ èmi kò kórìíra àwọn tó kórìíra rẹ? Ǹjẹ́ inú mi kò a sì bàjẹ́ sí àwọn tí ó dìde sí ọ?
Не мразя ли, Господи, ония, които мразят Тебе? И не гнуся ли се от ония, които се подигат против Тебе?
22 Èmi kórìíra wọn ní àkótán; èmi kà wọ́n sí ọ̀tá mi.
Със съвършена образа ги мразя, За неприятели ги имам.
23 Ọlọ́run, wádìí mi, kí o sì mọ ọkàn mí; dán mi wò, kí o sì mọ ìrò inú mi.
Изпитай ме, Боже, и познай сърцето ми; Опитай ме, и познай мислите ми;
24 Kí ó sì wò ó bí ipa ọ̀nà búburú kan bá wà nínú mi kí ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé ọ̀nà àìnípẹ̀kun.
И виж дали има в мене оскърбителен път; И води ме по вечен път.

< Psalms 139 >