< Psalms 138 >

1 Ti Dafidi. Èmi yóò yìn ọ́ tinútinú mi gbogbo; níwájú àwọn òrìṣà ni èmi ó kọrin ìyìn sí ọ.
Par David. Je te rendrai grâce de tout mon cœur. Devant les dieux, je chanterai tes louanges.
2 Èmi ó máa gbàdúrà sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀ èmi ó sì máa yin orúkọ rẹ nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ; nítorí ìwọ gbé ọ̀rọ̀ rẹ ga ju orúkọ rẹ lọ.
Je me prosternerai devant ton temple saint, et rendre grâce à ton Nom pour ta bonté et ta vérité; car tu as exalté ton Nom et ta Parole au-dessus de tout.
3 Ní ọjọ́ tí mo ké pè é ọ́, ìwọ dá mi lóhùn, ìwọ sì fi ipa mú mi lára le ní ọkàn mi.
Le jour où j'ai appelé, tu m'as répondu. Vous m'avez encouragé avec la force dans mon âme.
4 Gbogbo àwọn ọba ayé yóò yìn ọ́, Olúwa, ní ìgbà tí wọn bá gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ.
Tous les rois de la terre te rendront grâce, Yahvé, car ils ont entendu les paroles de ta bouche.
5 Nítòótọ́, wọn ó máa kọrin ní ipa ọ̀nà Olúwa; nítorí pé ńlá ni ògo Olúwa.
Oui, ils chanteront les voies de Yahvé, car la gloire de Yahvé est grande!
6 Bí Olúwa tilẹ̀ ga, síbẹ̀ ó júbà àwọn onírẹ̀lẹ̀; ṣùgbọ́n agbéraga ni ó mọ̀ ní òkèrè réré.
Car si Yahvé est élevé, il prend soin des humbles; mais il connaît l'orgueilleux de loin.
7 Bí èmi tilẹ̀ ń rìn nínú ìpọ́njú ìwọ ni yóò sọ mi di ààyè; ìwọ ó na ọwọ́ rẹ sí àwọn ọ̀tá mi, ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì gbà mí.
Quand je marche au milieu de la détresse, tu me fais revivre. Tu étendras ta main contre la colère de mes ennemis. Ta main droite me sauvera.
8 Olúwa yóò ṣe ohun tí ń ṣe tèmi láṣepé; Olúwa, àánú rẹ dúró láéláé; má ṣe kọ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ sílẹ̀.
L'Éternel accomplira ce qui me concerne. Ta bonté, Yahvé, dure à jamais. N'abandonnez pas le travail de vos propres mains.

< Psalms 138 >